< Psalms 92 >
1 A PSALM. A SONG FOR THE SABBATH DAY. [It is] good to give thanks to YHWH, And to sing praises to Your Name, O Most High,
Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2 To declare Your kindness in the morning, And Your faithfulness in the nights.
láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
3 On ten strings and on stringed instrument, On (higgaion) with harp.
lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
4 For You have caused me to rejoice, O YHWH, in Your work, I sing concerning the works of Your hands.
Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 How great Your works have been, O YHWH, Your thoughts have been very deep.
Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6 A brutish man does not know, And a fool does not understand this—
Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7 When the wicked flourish as an herb, And all workers of iniquity blossom—For their being destroyed forever and ever!
nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
8 And You [are] high for all time, O YHWH.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9 For behold, Your enemies, O YHWH, For behold, Your enemies perish, All workers of iniquity separate themselves.
Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
10 And You exalt my horn as a wild ox, I have been anointed with fresh oil.
Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11 And my eye looks on my enemies, Of those rising up against me, The evildoers, my ears hear.
Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
12 The righteous flourish as a palm-tree, He grows as a cedar in Lebanon.
Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
13 Those planted in the house of YHWH, In the courts of our God, flourish.
tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14 Still they bring forth in old age, They are fat and flourishing,
Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15 To declare that YHWH my Rock [is] upright, And there is no perverseness in Him!
láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”