< Psalms 47 >
1 TO THE OVERSEER. A PSALM OF THE SONS OF KORAH. All you peoples, clap the hand, Shout to God with a voice of singing,
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
2 For YHWH Most High [is] fearful, A great King over all the earth.
Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
3 He leads peoples under us, and nations under our feet.
Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
4 He chooses for us our inheritance, The excellence of Jacob that He loves. (Selah)
Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa, ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
5 God has gone up with a shout, YHWH with the sound of a horn.
Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀, Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.
6 Praise God—praise—give praise to our king, praise.
Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn. Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
7 For God [is] King of all the earth, Give praise, O understanding one.
Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé, ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
8 God has reigned over nations, God has sat on His holy throne,
Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí; Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
9 Nobles of peoples have been gathered, [With] the people of the God of Abraham, For the shields of earth [are] to God, Greatly has He been exalted!
Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni, òun ni ó ga jùlọ.