< Psalms 132 >

1 A SONG OF THE ASCENTS. Remember, YHWH, for David, all his afflictions;
Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
2 Who has sworn to YHWH, He has vowed to the Mighty One of Jacob:
Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
3 “If I enter into the tent of my house, If I go up on the couch of my bed,
Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
4 If I give sleep to my eyes, To my eyelids—slumber,
Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
5 Until I find a place for YHWH, dwelling places for the Mighty One of Jacob.”
títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
6 Behold, we have heard it in Ephratah, We have found it in the fields of the forest.
Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
7 We come into His dwelling places, We bow ourselves at His footstool.
Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
8 Arise, O YHWH, to Your rest, You, and the Ark of Your strength,
Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
9 Your priests put on righteousness, And Your pious ones cry aloud.
Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
10 For the sake of Your servant David, Do not turn back the face of Your anointed.
Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
11 YHWH has sworn truth to David, He does not turn back from it: “Of the fruit of your body, I set on the throne for you.
Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
12 If your sons keep My covenant, And My testimonies that I teach them, Their sons also forever and ever Sit on the throne for you.”
Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
13 For YHWH has fixed on Zion, He has desired [it] for a seat to Himself,
Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
14 “This [is] My rest forever and ever, Here I sit, for I have desired it.
Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
15 I greatly bless her provision, I satisfy her poor [with] bread,
Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
16 And I clothe her priests [with] salvation, And her pious ones sing aloud.
Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
17 There I cause a horn to spring up for David, I have arranged a lamp for My Anointed.
Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
18 I clothe His enemies [with] shame, And His crown flourishes on Him!”
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.

< Psalms 132 >