< Psalms 116 >

1 I have loved, because YHWH hears My voice, my supplication,
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Because He has inclined His ear to me, And during my days I call.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 Cords of death have surrounded me, And straits of Sheol have found me, I find distress and sorrow. (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 And in the Name of YHWH I call: Ah, now, O YHWH, deliver my soul,
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 YHWH [is] gracious, and righteous, Indeed, our God [is] merciful,
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 YHWH [is] a preserver of the simple, I was low, and He gives salvation to me.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Return, O my soul, to your rest, For YHWH has conferred benefits on you.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 For You have delivered my soul from death, My eyes from tears, my feet from overthrowing.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 I habitually walk before YHWH In the lands of the living.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 I have believed, for I speak, I have been greatly afflicted.
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 I said in my haste, “Every man [is] a liar.”
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 What do I return to YHWH? All His benefits [are] on me.
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 I lift up the cup of salvation, And in the Name of YHWH I call.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 Let me complete my vows to YHWH, Now, before all His people.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Precious in the eyes of YHWH [is] the death of His saints.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 Ah, now, O YHWH, for I [am] Your servant; I [am] Your servant, son of Your handmaid; You have opened my bonds.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 I sacrifice a sacrifice of thanks to You, And in the Name of YHWH I call.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 Let me complete my vows to YHWH, Now, before all His people,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 In the courts of the house of YHWH, In your midst, O Jerusalem, praise YAH!
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Psalms 116 >