< Psalms 115 >
1 Not to us, O YHWH, not to us, But to Your Name give glory, For Your kindness, for Your truth.
Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
2 Why do the nations say, “Where, pray, [is] their God?”
Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
3 And our God [is] in the heavens, All that He has pleased He has done.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
4 Their idols [are] silver and gold, work of man’s hands,
Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
5 They have a mouth, and they do not speak, They have eyes, and they do not see,
Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
6 They have ears, and they do not hear, They have a nose, and they do not smell,
Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
7 Their hands, but they do not handle, Their feet, and they do not walk;
Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
8 Nor do they mutter through their throat, Their makers are like them, Everyone who is trusting in them.
Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
9 O Israel, trust in YHWH, “He [is] their help and their shield.”
Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
10 O house of Aaron, trust in YHWH, “He [is] their help and their shield.”
Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
11 You fearing YHWH, trust in YHWH, “He [is] their help and their shield.”
Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
12 YHWH has remembered us, He blesses, He blesses the house of Israel, He blesses the house of Aaron,
Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
13 He blesses those fearing YHWH, The small with the great.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
14 YHWH adds to you—to you and to your sons.
Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
15 Blessed [are] you of YHWH, Maker of the heavens and earth,
Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
16 The heavens—the heavens [are] YHWH’s, And He has given the earth to sons of men;
Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
17 The dead do not praise YAH, Nor any going down to silence.
Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
18 And we, we bless YAH, From now on, and for all time. Praise YAH!
Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.