< Numbers 31 >
1 And YHWH speaks to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 “Execute the vengeance of the sons of Israel against the Midianites—afterward you are gathered to your people.”
“Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
3 And Moses speaks to the people, saying, “Arm men from [among] you for the war, and they are against Midian, to put the vengeance of YHWH on Midian;
Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
4 one thousand for a tribe—you send one thousand for a tribe, of all the tribes of Israel, to the war.”
Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
5 And there are given out of the thousands of Israel one thousand for a tribe—twelve thousand armed ones [for] war;
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
6 and Moses sends them, one thousand for a tribe, to the war; [he sent] them and Phinehas son of Eleazar the priest to the war, with the holy vessels and the trumpets of shouting in his hand.
Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
7 And they war against Midian, as YHWH has commanded Moses, and slay every male;
Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
8 and they have slain the kings of Midian besides their pierced ones: Evi, and Rekem, and Zur, and Hur, and Reba—five kings of Midian; and they have slain Balaam son of Beor with the sword.
Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
9 And the sons of Israel take the women of Midian and their infants captive; and they have plundered all their livestock, and all their substance, and all their wealth;
Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
10 and they have burned all their cities, with their habitations, and all their towers, with fire.
Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
11 And they take all the spoil and all the prey, among man and among beast;
Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
12 and they bring in the captives, and the prey, and the spoil to Moses, and to Eleazar the priest, and to the congregation of the sons of Israel, to the camp, to the plains of Moab, which [are] by the Jordan, [near] Jericho.
Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
13 And Moses, and Eleazar the priest, and all the princes of the congregation, go out to meet them, to the outside of the camp,
Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
14 and Moses is angry against the inspectors of the force, chiefs of the thousands, and chiefs of the hundreds, who are coming in from the warfare of battle.
Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
15 And Moses says to them, “Have you kept every female alive?
Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
16 Behold, they have been to the sons of Israel, through the word of Balaam, to cause a trespass against YHWH in the matter of Peor, and the plague is in the congregation of YHWH.
Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
17 And now, slay every male among the infants, indeed, slay every woman knowing a man by the lying of a male;
Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
18 and all the infants among the women who have not known the lying of a male you have kept alive for yourselves.
ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
19 And you, encamp at the outside of the camp [for] seven days; any who has slain a person, and any who has come against a pierced one, cleanse yourselves on the third day and on the seventh day—you and your captives;
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
20 and every garment, and every skin vessel, and every work of goats’ [hair], and every wooden vessel, you yourselves cleanse.”
Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
21 And Eleazar the priest says to the men of war who go to battle, “This [is] the statute of the law which YHWH has commanded Moses:
Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
22 only the gold, and the silver, the bronze, the iron, the tin, and the lead,
Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
23 everything which may go into fire, you cause to pass over through fire, and it has been clean; it is surely cleansed with the water of separation; and all that may not go into fire, you cause to pass over through water;
Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
24 and you have washed your garments on the seventh day and have been clean, and afterward you come into the camp.”
Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
25 And YHWH speaks to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
26 “Take up the sum of the prey of the captives, among man and among beast, you, and Eleazar the priest, and the heads of the fathers of the congregation;
“Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
27 and you have halved the prey between those handling the battle, who go out to the war, and all the congregation;
Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
28 and you have raised a tribute to YHWH from the men of battle, who go out to the war, one body out of five hundred, of man, and of the herd, and of the donkeys, and of the flock;
Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
29 you take from their half and have given [it] to Eleazar the priest [as] a raised-offering of YHWH.
Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
30 And from the sons of Israel’s half you take one possession out of fifty, of man, of the herd, of the donkeys, and of the flock, of all the livestock, and you have given them to the Levites keeping the charge of the Dwelling Place of YHWH.”
Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
31 And Moses does—Eleazar the priest also—as YHWH has commanded Moses.
Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
32 And the prey, the remainder of the spoil which the people of the host have spoiled, is six hundred thousand and seventy thousand and five thousand of the flock;
Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
33 and seventy-two thousand of the herd;
Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
34 and sixty-one thousand donkeys;
ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
35 and of mankind—of the women who have not known the lying of a male—all the persons [are] thirty-two thousand.
pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
36 And the half, the portion of those who go out into the war, is [in] number three hundred thousand and thirty thousand and seven thousand and five hundred of the flock.
Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
37 And the tribute to YHWH of the sheep is six hundred seventy-five;
Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
38 and the herd [is] thirty-six thousand, and their tribute to YHWH [is] seventy-two;
ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
39 and the donkeys [are] thirty thousand and five hundred, and their tribute to YHWH [is] sixty-one;
kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
40 and of mankind [are] sixteen thousand, and their tribute to YHWH [is] thirty-two persons.
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
41 And Moses gives the tribute—YHWH’s raised-offering—to Eleazar the priest, as YHWH has commanded Moses.
Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
42 And of the sons of Israel’s half, which Moses halved from the men who war—
Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
43 and the congregation’s half is three hundred thousand and thirty thousand [and] seven thousand and five hundred of the flock;
Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
44 and thirty-six thousand of the herd;
pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
45 and thirty thousand and five hundred donkeys;
tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
46 and sixteen thousand of mankind—
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
47 Moses takes from the sons of Israel’s half one possession from the fifty, of man and of beast, and gives them to the Levites keeping the charge of the Dwelling Place of YHWH, as YHWH has commanded Moses.
Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
48 And the inspectors whom the thousands of the host have (heads of the thousands and heads of the hundreds), draw near to Moses,
Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
49 and they say to Moses, “Your servants have taken up the sum of the men of war who [are] with us, and not a man of us has been missed;
Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
50 and we bring YHWH’s offering near, each of that which he has found of vessels of gold—chain, and bracelet, seal-ring, [ear]-ring, and bead—to make atonement for ourselves before YHWH.”
Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
51 And Moses receives—Eleazar the priest also—the gold from them, every vessel of workmanship;
Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
52 and all the gold of the raised-offering which they have lifted up to YHWH is sixteen thousand seven hundred and fifty shekels, from heads of the thousands and from heads of the hundreds;
Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
53 (the men of the host have each taken spoil for himself);
Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
54 and Moses takes—Eleazar the priest also—the gold from the heads of the thousands and of the hundreds, and they bring it into the Tent of Meeting [as] a memorial for the sons of Israel before YHWH.
Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.