< Numbers 26 >
1 And it comes to pass, after the plague, that YHWH speaks to Moses and to Eleazar son of Aaron the priest, saying,
Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-ààrùn Olúwa sọ fún Mose àti Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà pé,
2 “Take a census of all the congregation of the sons of Israel, from a son of twenty years and upward, by the house of their fathers, everyone going out to the host in Israel.”
“Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Israẹli.”
3 And Moses speaks—Eleazar the priest also—with them in the plains of Moab by the Jordan, [near] Jericho, saying,
Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Moabu pẹ̀lú Jordani tí ó kọjá Jeriko, Mose àti Eleasari àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,
4 “From a son of twenty years and upward,” as YHWH has commanded Moses and the sons of Israel who are coming out from the land of Egypt.
“Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ-ogun ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.” Èyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó jáde láti Ejibiti wá.
5 Reuben, firstborn of Israel—sons of Reuben: of Enoch [is] the family of the Enochite; of Pallu the family of the Palluite;
Àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli, láti ẹni ti ìdílé Hanoku, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hanoku ti jáde wá, láti ìdílé Pallu, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pallu ti jáde wá;
6 of Hezron the family of the Hezronite; of Carmi the family of the Carmite.
ti Hesroni, ìdílé àwọn ọmọ Hesroni; ti Karmi, ìdílé àwọn ọmọ Karmi.
7 These [are] families of the Reubenite, and their numbered ones are forty-three thousand and seven hundred and thirty.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Reubeni; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀sán ó dín àádọ́rin.
8 And the son of Pallu [is] Eliab;
Àwọn ọmọkùnrin Pallu ni Eliabu,
9 and the sons of Eliab [are] Nemuel, and Dathan, and Abiram; this [is that] Dathan and Abiram, called ones of the congregation, who have striven against Moses and against Aaron in the congregation of Korah, in their striving against YHWH,
àwọn ọmọkùnrin Elifelehu ni Nemueli àti Eliabu, Datani àti Abiramu. Èyí ni Datani àti Abiramu náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mose àti Aaroni tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kora nígbà tí wọ́n bá Olúwa jà.
10 and the earth opens her mouth, and swallows them and Korah, in the death of the congregation, in the fire consuming the two hundred and fifty men, and they become a sign;
Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kora, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́ta lé nígba ọkùnrin. Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.
11 but the sons of Korah did not die.
Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.
12 Sons of Simeon by their families: of Nemuel [is] the family of the Nemuelite; of Jamin the family of the Jaminite; of Jachin the family of the Jachinite;
Àwọn ọmọ ìran Simeoni bí ìdílé wọn: ti Nemueli, ìdílé Nemueli; ti Jamini, ìdílé Jamini; ti Jakini, ìdílé Jakini;
13 of Zerah the family of the Zerahite; of Shaul the family of the Shaulite.
ti Sera, ìdílé Sera; tí Saulu, ìdílé Saulu.
14 These [are] families of the Simeonite—twenty-two thousand and two hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Simeoni, ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba ọkùnrin.
15 Sons of Gad by their families: of Zephon [is] the family of the Zephonite; of Haggi the family of the Haggite; of Shuni the family of the Shunite;
Àwọn ọmọ Gadi bí ìdílé wọn: ti Sefoni, ìdílé Sefoni; ti Haggi, ìdílé Haggi; ti Ṣuni, ìdílé Ṣuni;
16 of Ozni the family of the Oznite; of Eri the family of the Erite:
ti Osni, ìdílé Osni; ti Eri, ìdílé Eri;
17 of Arod the family of the Arodite; of Areli the family of the Arelite.
ti Arodi, ìdílé Arodi; ti Areli, ìdílé Areli.
18 These [are] families of the sons of Gad by their numbered ones—forty thousand and five hundred.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gadi tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
19 Sons of Judah [are] Er and Onan; and Er dies—Onan also—in the land of Canaan.
Àwọn ọmọ Juda ni Eri àti Onani, ṣùgbọ́n Eri àti Onani kú ní ilẹ̀ Kenaani.
20 And sons of Judah by their families are: of Shelah the family of the Shelanite; of Perez the family of the Perezite; of Zerah the family of the Zerahite;
Àti àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣela, ìdílé Ṣela; ti Peresi, ìdílé Peresi; ti Sera, ìdílé Sera.
21 and sons of Perez are: of Hezron the family of the Hezronite; of Hamul the family of the Hamulite.
Àwọn ọmọ Peresi: ti Hesroni, ìdílé Hesroni; ti Hamulu, ìdílé Hamulu.
22 These [are] families of Judah by their numbered ones—seventy-six thousand and five hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé Juda; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
23 Sons of Issachar by their families: of Tola [is] the family of the Tolaite; of Pua the family of the Punite;
Àwọn ọmọ Isakari gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Tola, ìdílé Tola; ti Pufa, ìdílé Pufa;
24 of Jashub the family of the Jashubite; of Shimron the family of the Shimronite.
ti Jaṣubu, ìdílé Jaṣubu; ti Ṣimroni, ìdílé Ṣimroni.
25 These [are] families of Issachar by their numbered ones—sixty-four thousand and three hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé Isakari gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
26 Sons of Zebulun by their families: of Sered [is] the family of the Sardite; of Elon the family of the Elonite; of Jahleel the family of the Jahleelite.
Àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Seredi, ìdílé Seredi; ti Eloni, ìdílé Eloni; ti Jaleeli, ìdílé Jaleeli.
27 These [are] families of the Zebulunite by their numbered ones—sixty thousand and five hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
28 Sons of Joseph by their families [are] Manasseh and Ephraim.
Àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Manase àti Efraimu.
29 Sons of Manasseh: of Machir [is] the family of the Machirite; and Machir has begotten Gilead; of Gilead [is] the family of the Gileadite.
Àwọn ọmọ Manase: ti Makiri, ìdílé Makiri (Makiri sì bí Gileadi); ti Gileadi, ìdílé àwọn ọmọ Gileadi.
30 These [are] sons of Gilead: of Jeezer [is] the family of the Jeezerite; of Helek the family of the Helekite;
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi: ti Ieseri, ìdílé Ieseri; ti Heleki, ìdílé Heleki
31 and of Asriel the family of the Asrielite; and of Shechem the family of the Shechemite;
àti ti Asrieli, ìdílé Asrieli; àti ti Ṣekemu, ìdílé Ṣekemu;
32 and of Shemida the family of the Shemidaite; and of Hepher the family of the Hepherite.
àti Ṣemida, ìdílé àwọn ọmọ Ṣemida; àti ti Heferi, ìdílé àwọn ọmọ Heferi.
33 And Zelophehad son of Hepher had no sons, but [only] daughters, and the names of the daughters of Zelophehad [are] Mahlah, and Noah, Hoglah, Milcah, and Tirzah.
(Selofehadi ọmọ Heferi kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin ni Mahila, Noa, àti Hogla, Milka àti Tirsa).
34 These [are] families of Manasseh, and their numbered ones [are] fifty-two thousand and seven hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé Manase tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
35 These [are] sons of Ephraim by their families: of Shuthelah [is] the family of the Shuthelhite; of Becher the family of the Bachrite; of Tahan the family of the Tahanite.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: láti ọ̀dọ̀ Ṣutelahi, ìdílé àwọn ọmọ Ṣutelahi; ti Bekeri, ìdílé àwọn ọmọ Bekeri; ti Tahani, ìdílé àwọn ọmọ Tahani.
36 And these [are] sons of Shuthelah: of Eran the family of the Eranite.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣutelahi: ti Erani, ìdílé àwọn ọmọ Erani.
37 These [are] families of the sons of Ephraim by their numbered ones—thirty-two thousand and five hundred. These [are] sons of Joseph by their families.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Efraimu, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
38 Sons of Benjamin by their families: of Bela [is] the family of the Belaite; of Ashbel the family of the Ashbelite; of Ahiram the family of the Ahiramite;
Àwọn ọmọ Benjamini gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nìyìí: tí Bela, ìdílé àwọn ọmọ Bela; ti Aṣbeli, ìdílé àwọn ọmọ Aṣbeli; ti Ahiramu, ìdílé àwọn ọmọ Ahiramu;
39 of Shupham the family of the Shuphamite; of Hupham the family of the Huphamite.
ti Ṣufamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣufamu; ti Hufamu, ìdílé àwọn ọmọ Hufamu.
40 And sons of Bela are Ard and Naaman: [of Ard is] the family of the Ardite; of Naaman the family of the Naamite.
Àwọn ọmọ Bela ní ipasẹ̀ Ardi àti Naamani nìyìí: ti Ardi, ìdílé àwọn ọmọ Ardi; ti Naamani, ìdílé àwọn ọmọ Naamani.
41 These [are] sons of Benjamin by their families, and their numbered ones [are] forty-five thousand and six hundred.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Benjamini; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ.
42 These [are] sons of Dan by their families: of Shuham [is] the family of the Shuhamite; these [are] families of Dan by their families;
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣuhamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu. Wọ̀nyí ni ìdílé Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
43 all the families of the Shuhamite by their numbered ones—sixty-four thousand and four hundred.
Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
44 Sons of Asher by their families: of Jimna [is] the family of the Jimnite; of Jesui the family of the Jesuite; of Beriah the family of the Beriite.
Ti àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Imina, ìdílé àwọn ọmọ Imina; ti Iṣfi, ìdílé àwọn ọmọ Iṣfi; ti Beriah, ìdílé àwọn ọmọ Berii.
45 Of sons of Beriah: of Heber [is] the family of the Heberite; of Malchiel the family of the Malchielite.
Ti àwọn ọmọ Beriah: ti Heberi, ìdílé àwọn ọmọ Heberi; ti Malkieli, ìdílé àwọn ọmọ Malkieli.
46 And the name of the daughter of Asher [is] Sarah.
(Orúkọ ọmọ Aṣeri obìnrin nì jẹ́ Sera.)
47 These [are] families of the sons of Asher by their numbered ones—fifty-three thousand and four hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
48 Sons of Naphtali by their families: of Jahzeel [is] the family of the Jahzeelite; of Guni the family of the Gunite;
Ti àwọn ọmọ Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Jasieli, ìdílé àwọn ọmọ Jaseeli: ti Guni, ìdílé àwọn ọmọ Guni;
49 of Jezer the family of the Jezerite; of Shillem the family of the Shillemite.
ti Jeseri, ìdílé àwọn ọmọ Jeṣeri; ti Ṣillemu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣillemu.
50 These [are] families of Naphtali by their families, and their numbered ones [are] forty-five thousand and four hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé ti Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbèje.
51 These [are] numbered ones of the sons of Israel—six hundred thousand and one thousand seven hundred and thirty.
Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé ẹgbẹ̀sán dín làádọ́rin.
52 And YHWH speaks to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
53 “The land is apportioned to these by inheritance, by the number of names;
“Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn.
54 to the many you increase their inheritance, and to the few you diminish their inheritance; each is given his inheritance according to his numbered ones.
Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.
55 Surely the land is apportioned by lot; they inherit by the names of the tribes of their fathers;
Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni í.
56 their inheritance is apportioned according to the lot between many and few.”
Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrín ńlá àti kékeré.”
57 And these [are] numbered ones of the Levite by their families: of Gershon [is] the family of the Gershonite; of Kohath the family of the Kohathite; of Merari the family of the Merarite.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Lefi tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Gerṣoni, ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni; ti Kohati, ìdílé àwọn ọmọ Kohati; ti Merari, ìdílé àwọn ọmọ Merari.
58 These [are] families of the Levite: the family of the Libnite, the family of the Hebronite, the family of the Mahlite, the family of the Mushite, the family of the Korathite. And Kohath has begotten Amram,
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Lefi; ìdílé àwọn ọmọ Libni, ìdílé àwọn ọmọ Hebroni, ìdílé àwọn ọmọ Mahili, ìdílé àwọn ọmọ Muṣi, ìdílé àwọn ọmọ Kora. (Kohati ni baba Amramu,
59 and the name of Amram’s wife is Jochebed, daughter of Levi, whom has been born to Levi in Egypt; and she bears to Amram Aaron, and Moses, and their sister Miriam.
orúkọ aya Amramu sì ń jẹ́ Jokebedi, ọmọbìnrin Lefi, tí ìyá rẹ̀ bí fún Lefi ní Ejibiti. Òun sì bí Aaroni, Mose, àti Miriamu arábìnrin wọn fún Amramu.
60 And born to Aaron [are] Nadab, and Abihu, Eleazar, and Ithamar;
Aaroni ni baba Nadabu àti Abihu, Eleasari àti Itamari.
61 and Nadab dies—Abihu also—in their bringing strange fire near before YHWH.
Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)
62 And their numbered ones are twenty-three thousand, every male from a son of a month and upwards, for they have not numbered themselves in the midst of the sons of Israel, because an inheritance has not been given to them in the midst of the sons of Israel.
Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Lefi láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀rún. Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.
63 These [are] those numbered by Moses and Eleazar the priest, who have numbered the sons of Israel in the plains of Moab by the Jordan, [near] Jericho;
Àwọn wọ̀nyí ni Mose àti Eleasari àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jordani létí Jeriko.
64 and among these there has not been a man of those numbered by Moses and Aaron the priest, who numbered the sons of Israel in the wilderness of Sinai,
Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mose àti Aaroni àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní aginjù Sinai.
65 for YHWH said of them, “They certainly die in the wilderness”; and there has not been left a man of them, except Caleb son of Jephunneh and Joshua son of Nun.
Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kíkú ni wọn yóò kú sí aginjù, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú àfi Kalebu ọmọ Jefunne, àti Joṣua ọmọ Nuni.