< Numbers 1 >

1 And YHWH speaks to Moses in the wilderness of Sinai, in the Tent of Meeting, on the first of the second month, in the second year of their going out of the land of Egypt, saying,
Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
2 “Take a census of all the congregation of the sons of Israel by their families, by the house of their fathers, in the number of names—every male by their counted heads;
“Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
3 from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host in Israel, you number them by their hosts, you and Aaron;
Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
4 and with you there is a man for a tribe, each is a head of the house of his fathers.
Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
5 And these [are] the names of the men who stand with you: for Reuben, Elizur son of Shedeur;
“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
6 for Simeon, Shelumiel son of Zurishaddai;
Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
7 for Judah, Nahshon son of Amminadab;
Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
8 for Issachar, Nathaneel son of Zuar;
Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
9 for Zebulun, Eliab son of Helon;
Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
10 for the sons of Joseph: for Ephraim, Elishama son of Ammihud; for Manasseh, Gamaliel son of Pedahzur;
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
11 for Benjamin, Abidan son of Gideoni;
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
12 for Dan, Ahiezer son of Ammishaddai;
Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
13 for Asher, Pagiel son of Ocran;
Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
14 for Gad, Eliasaph son of Deuel;
Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
15 for Naphtali, Ahira son of Enan.”
Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
16 These [are] those called of the congregation, princes of the tribes of their fathers; they [are] heads of the thousands of Israel.
Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
17 And Moses takes—Aaron also—these men, who were defined by name,
Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
18 and they assembled all the congregation on the first of the second month, and they declare their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names from a son of twenty years and upward, by their counted heads,
wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
19 as YHWH has commanded Moses; and he numbers them in the wilderness of Sinai.
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
20 And the sons of Reuben, Israel’s firstborn—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, by their counted heads, every male from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
21 their numbered ones, for the tribe of Reuben, are forty-six thousand and five hundred.
Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
22 Of the sons of Simeon—their births, by their families, by the house of their fathers, its numbered ones in the number of names, by their counted heads, every male from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
23 their numbered ones, for the tribe of Simeon, [are] fifty-nine thousand and three hundred.
Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
24 Of the sons of Gad—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
25 their numbered ones, for the tribe of Gad, [are] forty-five thousand and six hundred and fifty.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
26 Of the sons of Judah—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
27 their numbered ones, for the tribe of Judah, [are] seventy-four thousand and six hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
28 Of the sons of Issachar—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
29 their numbered ones, for the tribe of Issachar, [are] fifty-four thousand and four hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
30 Of the sons of Zebulun—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
31 their numbered ones, for the tribe of Zebulun, [are] fifty-seven thousand and four hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
32 Of the sons of Joseph: of the sons of Ephraim—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
33 their numbered ones, for the tribe of Ephraim, [are] forty thousand and five hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
34 Of the sons of Manasseh—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
35 their numbered ones, for the tribe of Manasseh, [are] thirty-two thousand and two hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
36 Of the sons of Benjamin—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
37 their numbered ones, for the tribe of Benjamin, [are] thirty-five thousand and four hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
38 Of the sons of Dan—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
39 their numbered ones, for the tribe of Dan, [are] sixty-two thousand and seven hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
40 Of the sons of Asher—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
41 their numbered ones, for the tribe of Asher, [are] forty-one thousand and five hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
42 Of the sons of Naphtali—their births, by their families, by the house of their fathers, in the number of names, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host—
Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
43 their numbered ones, for the tribe of Naphtali, [are] fifty-three thousand and four hundred.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
44 These [are] those numbered, whom Moses numbered—Aaron also—and the princes of Israel, twelve men, each one has been [the representative] for the house of his fathers.
Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
45 And they are, all those numbered of the sons of Israel, by the house of their fathers, from a son of twenty years and upward, everyone going out to the host in Israel,
Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
46 indeed, all those numbered are six hundred thousand and three thousand and five hundred and fifty.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
47 And the Levites, for the tribe of their fathers, have not numbered themselves in their midst,
A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
48 seeing YHWH speaks to Moses, saying,
Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
49 “Only the tribe of Levi you do not number, and you do not take up their census in the midst of the sons of Israel;
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
50 and you, appoint the Levites over the Dwelling Place of the Testimony, and over all its vessels, and over all that it has; they carry the Dwelling Place, and all its vessels, and they serve it; and they encamp around the Dwelling Place.
Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
51 And in the journeying of the Dwelling Place, the Levites take it down, and in the encamping of the Dwelling Place, the Levites raise it up; and the stranger who is coming near is put to death.”
Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
52 And the sons of Israel have encamped, each by his camp, and each by his standard, by their hosts;
kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
53 and the Levites encamp around the Dwelling Place of the Testimony; and there is no wrath on the congregation of the sons of Israel, and the Levites have kept the charge of the Dwelling Place of the Testimony.
Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
54 And the sons of Israel do according to all that YHWH has commanded Moses; so they have done.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Numbers 1 >