< Nehemiah 11 >
1 And the heads of the people dwell in Jerusalem, and the rest of the people have caused lots to fall to bring in one out of ten to dwell in Jerusalem the holy city, and nine parts in the cities,
Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn.
2 and the people give a blessing to all the men who are offering themselves willingly to dwell in Jerusalem.
Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.
3 And these [are] heads of the province who have dwelt in Jerusalem, and in cities of Judah, they have dwelt each in his possession in their cities; Israel, the priests, and the Levites, and the Nethinim, and the sons of the servants of Solomon.
Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà.
4 And in Jerusalem have dwelt of the sons of Judah, and of the sons of Benjamin. Of the sons of Judah: Athaiah son of Uzziah, son of Zechariah, son of Amariah, son of Shephatiah, son of Mahalaleel, of the sons of Perez;
Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu). Nínú àwọn ọmọ Juda: Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;
5 and Masseiah son of Baruch, son of Col-Hozeh, son of Hazaiah, son of Adaiah, son of Joiarib, son of Zechariah, son of Shiloni;
àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.
6 all the sons of Perez who are dwelling in Jerusalem [are] four hundred sixty-eight, men of valor.
Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rinlénírinwó ó dín méjì alágbára ọkùnrin.
7 And these [are] sons of Benjamin: Sallu son of Meshullam, son of Joed, son of Pedaiah, son of Kolaiah, son of Maaseiah, son of Ithiel, son of Jesaiah;
Nínú àwọn ìran Benjamini: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joẹdi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah,
8 and after him Gabbai, Sallai, nine hundred twenty-eight.
àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rún ó lé mẹ́jọ ọkùnrin.
9 And Joel son of Zichri [is] inspector over them, and Judah son of Senuah [is] over the city—second.
Joẹli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.
10 Of the priests: Jedaiah son of Joiarib, Jachin,
Nínú àwọn àlùfáà: Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;
11 Seraiah son of Hilkiah, son of Meshullam, son of Zadok, son of Meraioth, son of Ahitub, leader of the house of God,
Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run,
12 and their brothers doing the work of the house [are] eight hundred twenty-two; and Adaiah son of Jeroham, son of Pelaliah, son of Amzi, son of Zechariah, son of Pashhur, son of Malchiah,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó lé mẹ́rìnlélógún ọkùnrin: Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,
13 and his brothers, heads of fathers, two hundred forty-two; and Amashsai son of Azareel, son of Ahazai, son of Meshillemoth, son of Immer,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó lé méjì ọkùnrin: Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri,
14 and their brothers, one hundred twenty-eight mighty men of valor; and an inspector over them [is] Zabdiel, son of [one of] the great men.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjìdínláàádóje. Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.
15 And of the Levites: Shemaiah son of Hashub, son of Azrikam, son of Hashabiah, son of Bunni,
Láti inú àwọn ọmọ Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;
16 and Shabbethai, and Jozabad, [are] over the outward work of the house of God, of the heads of the Levites,
Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;
17 and Mattaniah son of Micha, son of Zabdi, son of Asaph, [is] head—at the commencement he gives thanks in prayer; and Bakbukiah [is] second among his brothers, and Abda son of Shammua, son of Galal, son of Jeduthun.
Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà; Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀; àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.
18 All the Levites, in the holy city, [are] two hundred eighty-four.
Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́rin.
19 And the gatekeepers, Akkub, Talmon, and their brothers, those watching at the gates, [are] one hundred seventy-two.
Àwọn aṣọ́nà: Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàádọ́sàn-án ọkùnrin.
20 And the rest of Israel, of the priests, of the Levites, [are] in all cities of Judah, each in his inheritance;
Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.
21 and the Nethinim are dwelling in Ophel, and Ziha and Gishpa [are] over the Nethinim.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Siha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.
22 And the overseer of the Levites in Jerusalem [is] Uzzi son of Bani, son of Hashabiah, son of Mattaniah, son of Micha—of the sons of Asaph, the singers [who are] for the front of the work of the house of God,
Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run.
23 for the command of the king [is] on them, and support [is] for the singers, a matter of a day in its day.
Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.
24 And Pethahiah son of Meshezabeel, of the sons of Zerah, son of Judah, [is] by the hand of the king, for every matter of the people.
Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.
25 And at the villages with their fields, of the sons of Judah there have dwelt, in Kirjath-Arba and its small towns, and in Dibon and its small towns, and in Jekabzeel and its villages,
Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli.
26 and in Jeshua, and in Moladah, and in Beth-Phelet,
Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti
27 and in Hazar-Shaul, and in Beer-Sheba and its small towns,
ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀.
28 and in Ziklag, and in Mekonah and in its small towns,
Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀,
29 and En-Rimmon, and in Zareah, and in Jarmuth,
ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu,
30 Zanoah, Adullam, and their villages, Lachish and its fields, Azekah and its small towns; and they encamp from Beer-Sheba to the Valley of Hinnom.
Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé àfonífojì Hinnomu.
31 And sons of Benjamin [are] at Geba, Michmash, and Aija, and Beth-El, and its small towns,
Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀.
32 Anathoth, Nob, Ananiah,
Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah,
33 Hazor, Ramah, Gittaim,
ní Hasori Rama àti Gittaimu,
34 Hadid, Zeboim, Neballat,
ní Hadidi, Seboimu àti Neballati,
35 Lod, and Ono, the Valley of the Craftsmen.
ní Lodi àti Ono, àti ní àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.
36 And of the Levites, the divisions of Judah [are] for Benjamin.
Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.