< Lamentations 5 >

1 Remember, O YHWH, what has befallen us, Look attentively, and see our reproach.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Our inheritance has been turned to strangers, Our houses to foreigners.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Orphans we have been—without a father, our mothers [are] as widows.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 We have drunk our water for money, Our wood comes for a price.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 For our neck we have been pursued, We have labored—there has been no rest for us.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 [To] Egypt we have given a hand, [To] Asshur, to be satisfied with bread.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Our fathers have sinned—they are not, We have borne their iniquities.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Servants have ruled over us, There is no deliverer from their hand.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 With our lives we bring in our bread, Because of the sword of the wilderness.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Our skin as an oven has been burning, Because of the raging of the famine.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Wives in Zion they have humbled, Virgins—in cities of Judah.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Princes have been hanged by their hand, Elderly faces have not been honored.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 They have taken young men to grind, And youths have stumbled with wood.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Elderly have ceased from the gate, Young men from their song.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 The joy of our heart has ceased, Our dancing has been turned to mourning.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 The crown has fallen [from] our head, Woe [is] now to us, for we have sinned.
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Our heart has been sick for this, Our eyes have been dim for these.
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 For the Mount of Zion—that is desolate, Foxes have gone up on it.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 You, O YHWH, remain for all time, Your throne to generation and generation.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Why do You forget us forever? You forsake us for [the] length of [our] days!
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Turn us back, O YHWH, to You, And we turn back, renew our days as of old.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 For have You utterly rejected us? You have been angry against us—exceedingly?
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentations 5 >