< Joshua 12 >

1 And these [are] kings of the land whom the sons of Israel have struck, and possess their land beyond the Jordan, at the sun-rising, from the Brook of Arnon to Mount Hermon, and all the plain eastward:
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
2 Sihon, king of the Amorite, who is dwelling in Heshbon, ruling from Aroer which [is] on the border of the Brook of Arnon, and the middle of the brook, and half of Gilead, and to the Brook of Jabok, the border of the sons of Ammon;
Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
3 and the plain to the Sea of Chinneroth eastward, and to the Sea of the Plain (the Salt Sea) eastward, the way to Beth-Jeshimoth, and from the south under the Springs of Pisgah.
Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
4 And the border of Og king of Bashan (of the remnant of the Rephaim), who is dwelling in Ashtaroth and in Edrei,
Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
5 and ruling in Mount Hermon, and in Salcah, and in all Bashan, to the border of the Geshurite, and the Maachathite, and the half of Gilead, the border of Sihon king of Heshbon.
Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
6 Moses, servant of YHWH, and the sons of Israel have struck them, and Moses, servant of YHWH, gives it—a possession to the Reubenite, and to the Gadite, and to the half of the tribe of Manasseh.
Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
7 And these [are] kings of the land whom Joshua and the sons of Israel have struck beyond the Jordan westward, from Ba‘al-Gad, in the Valley of Lebanon, and to the Mount of Halak, which is going up to Seir; and Joshua gives it to the tribes of Israel—a possession according to their divisions;
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
8 in the hill-country, and in the low country, and in the plain, and in the springs, and in the wilderness, and in the south; the Hittite, the Amorite, and the Canaanite, the Perizzite, the Hivite, and the Jebusite:
ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
9 the king of Jericho, one; the king of Ai, which [is] beside Bethel, one;
Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
10 the king of Jerusalem, one; the king of Hebron, one;
ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
11 the king of Jarmuth, one; the king of Lachish, one;
ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
12 the king of Eglon, one; the king of Gezer, one;
ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
13 the king of Debir, one; the king of Geder, one;
ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
14 the king of Hormah, one; the king of Arad, one;
ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
15 the king of Libnah, one; the king of Adullam, one;
ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
16 the king of Mekkedah, one; the king of Beth-El, one;
ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
17 the king of Tappuah, one; the king of Hepher, one;
ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
18 the king of Aphek, one; the king of Lasharon, one;
ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
19 the king of Madon, one; the king of Hazor, one;
ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
20 the king of Shimron-Meron, one; the king of Achshaph, one;
ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
21 the king of Taanach, one; the king of Megiddo, one;
ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
22 the king of Kedesh, one; the king of Jokneam of Carmel, one;
ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
23 the king of Dor, at the elevation of Dor, one; the king of the nations of Gilgal, one;
ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
24 the king of Tirzah, one; all the kings [are] thirty-one.
ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.

< Joshua 12 >