< Jeremiah 51 >

1 Thus said YHWH: “Behold, I am stirring up against Babylon, And the inhabitants of Leb, My withstanders, A destroying wind,
Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
2 And I have sent fanners to Babylon, And they have fanned her, and they empty her land, For they have been against her, All around—in the day of evil.
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
3 Do not let the treader tread his bow, Nor lift himself up in his coat of mail, Nor have pity on her young men, Devote all her host to destruction.
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
4 And the wounded have fallen in the land of the Chaldeans, And the pierced-through in her streets.
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
5 For Israel and Judah are not forsaken By his God—by YHWH of Hosts, For their land has been full of guilt, Against the Holy One of Israel.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
6 Flee from the midst of Babylon, And let each deliver his soul, Do not be cut off in her iniquity, For it [is] a time of vengeance for YHWH—His, He is rendering repayment to her.
“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
7 Babylon [is] a golden cup in the hand of YHWH, Making all the earth drunk, Nations have drunk of her wine, Therefore nations boast themselves.
Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
8 Babylon has suddenly fallen, Indeed, she is broken, howl for her, Take balm for her pain, perhaps she may be healed.
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
9 We healed Babylon, and she was not healed, Forsake her, and we go, each to his land, For her judgment has come to the heavens, And it has been lifted up to the clouds.
“‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
10 YHWH has brought forth our righteousnesses, Come, and we recount in Zion the work of our God YHWH.
“‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
11 Cleanse the arrows, fill the shields, YHWH has stirred up the spirit of the kings of Media, For His purpose [is] against Babylon to destroy her, For it [is] the vengeance of YHWH, The vengeance of His temple.
“Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 Lift up an ensign to the walls of Babylon, Strengthen the watch, Establish the watchers, prepare the ambush, For YHWH has both devised and done that which He spoke, Concerning the inhabitants of Babylon.
Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 O dweller on many waters, abundant in treasures, Your end has come—the measure of your dishonest gain.
Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 YHWH of Hosts has sworn by Himself, That, Surely I have filled you [with] men as the cankerworm, And they have cried against you—shouting.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
15 Making [the] earth by His power, Establishing [the] world by His wisdom, Who by His understanding stretched out the heavens,
“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 At the voice He gives forth, A multitude of waters [are] in the heavens, And He causes vapors to come up from the end of the earth, He has made lightnings for rain, And He brings out wind from His treasures.
Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
17 Every man has been brutish by knowledge, Everyone has been put to shame—from refining a carved image, For his molten image [is] falsehood, And there is no breath in them.
“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
18 They [are] vanity—a work of errors, They perish in the time of their inspection.
Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 The Portion of Jacob [is] not like these, For He is forming the whole, And [Israel is] the tribe of His inheritance, YHWH of Hosts [is] His Name.
Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
20 You [are] My shatterer—weapons of war, And I have broken in pieces nations by you, And I have destroyed kingdoms by you,
“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 And I have broken in pieces horse and its rider by you, And I have broken in pieces chariot and its charioteer by you,
Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
22 And I have broken in pieces man and woman by you, And I have broken in pieces old and young by you, And I have broken in pieces young man and virgin by you,
pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 And I have broken in pieces shepherd and his drove by you, And I have broken in pieces farmer and his team by you, And I have broken in pieces governors and prefects by you.
Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
24 And I have repaid to Babylon, And to all inhabitants of Chaldea, All the evil that they have done in Zion, Before your eyes,” a declaration of YHWH.
“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
25 “Behold, I [am] against you, O destroying mountain,” A declaration of YHWH, “That is destroying all the earth, And I have stretched out My hand against you, And I have rolled you from the rocks, And given you for a burnt mountain.
“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 And they do not take out of you a stone for a corner, And a stone for foundations, For you are continuous desolations,” A declaration of YHWH.
A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
27 “Lift up an ensign in the land, Blow a horn among nations, Sanctify nations against it, Summon against it the kingdoms of Ararat, Minni, and Ashkenaz, Appoint an infant head against it, Cause the horse to ascend as the rough cankerworm.
“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 Sanctify against it the nations with the kings of Media, Its governors and all its prefects, And all the land of its dominion.
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 And the land shakes, and it is pained, For the purposes of YHWH have stood against Babylon, To make the land of Babylon a desolation without inhabitant.
Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 The mighty of Babylon have ceased to fight, They have remained in strongholds, Their might has failed, they have become [as] women, They have burned her dwelling places, Her bars have been broken.
Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Runner runs to meet runner, And announcer to meet announcer, To announce to the king of Babylon, For his city has been captured—at the extremity.
Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 And the passages have been captured, And they have burned the reeds with fire, And the men of war have been troubled.
Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
33 For thus said YHWH of Hosts, God of Israel: The daughter of Babylon [is] as a threshing-floor, The time of her threshing—yet a little [while], And the time of her harvest has come.
Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
34 Devoured us, crushed us, has Nebuchadnezzar king of Babylon, He has set us [as] an empty vessel, He has swallowed us as a dragon, He has filled his belly with my delicacies, He has driven us away.
“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 My wrong, and [that of] my flesh, [is] on Babylon—The inhabitant of Zion says; And my blood [is] on the inhabitants of Chaldea—Jerusalem says.
Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
36 Therefore, thus said YHWH: Behold, I am pleading your cause, And I have avenged your vengeance, And dried up her sea, and made her fountains dry.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 And Babylon has been for heaps, A habitation of dragons, An astonishment, and a hissing, without inhabitant.
Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 They roar together as young lions, They have shaken themselves as lions’ whelps.
Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
39 In their heat I make their banquets, And I have caused them to drink, so that they exult, And have slept a continuous sleep, And do not awaken,” a declaration of YHWH.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
40 “I cause them to go down as lambs to slaughter, As rams with male goats.
“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
41 How Sheshach has been captured, Indeed, the praise of the whole earth is caught, How Babylon has been for an astonishment among nations.
“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 The sea has come up over Babylon, She has been covered with a multitude of its billows.
Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Her cities have been for a desolation, A dry land, and a wilderness, A land—none dwell in them, Nor does a son of man pass over into them.
Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 And I have seen after Bel in Babylon, And I have brought forth that which he swallowed—from his mouth, And nations no longer flow to him, Also the wall of Babylon has fallen.
Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
45 Go forth from her midst, O My people, And let each deliver his soul, Because of the fierceness of the anger of YHWH,
“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
46 And lest your heart be tender, And you are afraid of the report that is heard in the land, And the report has come in [one] year, And after it [another] report in [another] year, And violence [is] in the land, ruler against ruler;
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 Therefore, behold, days are coming, And I have seen after the carved images of Babylon. And all its land is ashamed, And all its pierced ones fall in its midst.
Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 And heavens and earth and all that [is] in them Have cried aloud against Babylon, For the spoilers come to her from the north,” A declaration of YHWH.
Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
49 “As Babylon [has caused the] pierced of Israel to fall, So they of Babylon have fallen, You pierced of all the earth.
“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 You escaped of the sword, go on, do not stand, Remember YHWH from afar, And let Jerusalem come up on your heart.
Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
51 We have been ashamed, for we heard reproach, Shame has covered our faces, For strangers have come in against the sanctuaries of the house of YHWH.
“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
52 Therefore, behold, days are coming,” A declaration of YHWH, “And I have seen after her carved images, And the wounded groan in all her land.
“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
53 Because Babylon goes up to the heavens, And because she fortifies the high place of her strength, Spoilers come into her from Me,” A declaration of YHWH.
Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
54 “A voice of a cry [is] from Babylon, And of great destruction from the land of the Chaldean.
“Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 For YHWH is spoiling Babylon, And has destroyed her great voice, And her billows have sounded as many waters, Their voice has given forth a noise.
Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 For a spoiler has come in against her—against Babylon, And her mighty ones have been captured, Their bows have been broken, For the God of recompenses—YHWH—certainly repays.
Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
57 And I have caused her princes to drink, And her wise men, her governors, And her prefects, and her mighty ones, And they have slept a continuous sleep, And they do not awaken—an affirmation of the King, YHWH of Hosts [is] His Name.
Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
58 Thus said YHWH of Hosts: The wall of Babylon—The broad one—is made utterly bare, And her high gates are burned with fire, And peoples labor in vain, And nations in fire, and have been weary!”
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
59 The word that Jeremiah the prophet has commanded Seraiah son of Neriah, son of Maaseiah, in his going with Zedekiah king of Judah to Babylon, in the fourth year of his reign—and Seraiah [is] a quiet prince;
Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
60 and Jeremiah writes all the calamity that comes to Babylon on one scroll—all these words that are written concerning Babylon.
Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
61 And Jeremiah says to Seraiah, “When you enter Babylon, then you have seen, and have read all these words,
Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
62 and have said: YHWH, You have spoken concerning this place, to cut it off, that there is none dwelling in it, from man even to livestock, for it is a continuous desolation.
Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
63 And it has come to pass, when you finish reading this scroll, you bind a stone to it, and have cast it into the midst of the Euphrates,
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
64 and said, Thus Babylon sinks, and she does not arise, because of the calamity that I am bringing in against it, and they have been weary.” Until now [are the] words of Jeremiah.
Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

< Jeremiah 51 >