< Jeremiah 21 >
1 The word that has been to Jeremiah from YHWH, in King Zedekiah’s sending to him Pashhur son of Malchiah and Zephaniah son of Maaseiah the priest, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 “Please inquire of YHWH for us, for Nebuchadnezzar king of Babylon has fought against us; perhaps YHWH deals with us according to all His wonders, and causes him to go up from off us.”
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 And Jeremiah says to them, “Thus you say to Zedekiah,
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Thus said YHWH, God of Israel: Behold, I am turning around the weapons of battle That [are] in your hand, With which you fight the king of Babylon, And the Chaldeans, who are laying siege against you, At the outside of the wall, And I have gathered them into the midst of this city,
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 And I have fought against you, With an outstretched hand, and with a strong arm, And in anger, and in fury, and in great wrath,
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 And I have struck the inhabitants of this city, Both man and beast, They die by a great pestilence.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 And after this,” A declaration of YHWH, “I give Zedekiah king of Judah, And his servants, and the people, And those left in this city, From the pestilence, from the sword, and from the famine, Into the hand of Nebuchadnezzar king of Babylon, And into the hand of their enemies, And into the hand of those seeking their life, And he has struck them by the mouth of the sword, He has no pity on them, Nor does he spare, nor does he have mercy.”
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 “And you say to this people, Thus said YHWH: Behold, I am setting before you the way of life, And the way of death!
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Whoever is abiding in this city—dies, By sword, and by famine, and by pestilence, And whoever is going forth, And has fallen to the Chaldeans, Who are laying siege against you—lives, And his life has been for a spoil to him.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 For I have set My face against this city for calamity, And not for good,” A declaration of YHWH. “It is given into the hand of the king of Babylon, And he has burned it with fire.
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 And as for the house of the king of Judah,” Hear a word of YHWH;
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 O house of David, thus said YHWH: “Decide judgment in the morning, And deliver the plundered from the hand of the oppressor, Lest My fury go forth as fire, And has burned, and none is quenching, Because of the evil of your doings.
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Behold, I [am] against you,” A declaration of YHWH, “O inhabitant of the valley, rock of the plain, Who are saying, Who comes down against us? And who comes into our habitations?
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 And I have laid a charge against you, According to the fruit of your doings,” A declaration of YHWH, “And I have kindled a fire in its forest, And it has consumed all its outskirts!”
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”