< Isaiah 27 >
1 In that day YHWH lays a charge, With His sword—the sharp, and the great, and the strong, On leviathan—a fleeing serpent, And on leviathan—a crooked serpent, And He has slain the dragon that [is] in the sea.
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì, Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì; Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
2 In that day respond to her, “A desirable vineyard,
Ní ọjọ́ náà, “Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
3 I, YHWH, am its keeper, I water it every moment, Lest any lay a charge against it, Night and day I keep it!
Èmi Olúwa ń bojútó o, Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà. Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
4 Fury is not in Me; Who gives Me a brier—a thorn in battle? I step into it, I burn it at once.
Inú kò bí mi. Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí! Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun, Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
5 Or—he takes hold on My strength, [That] he makes peace with Me, [And] he makes peace with Me.”
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò; jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
6 He causes those coming in to take root, Jacob blossoms, and Israel has flourished, And they have filled the face of the world [with] increase.
Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò, Israẹli yóò tanná yóò sì rudi èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
7 Has He struck him as the striking of his striker? Does He slay as the slaying of his slain?
Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀? Ǹjẹ́ a ti pa á gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
8 In measure, in sending it forth, you strive with it, He has taken away by His sharp wind, In the day of an east wind,
Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó fi dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
9 Therefore the iniquity of Jacob is covered by this, And this [is] all the fruit—To take away his sin, In his setting all the stones of an altar, As chalkstones beaten in pieces, They do not rise—Asherim and images.
Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu, èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́, kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí tí yóò wà ní ìdúró.
10 For the fortified city [is] alone, A habitation cast out and forsaken as a wilderness, There the calf delights, And there it lies down, And has consumed its branches.
Ìlú olódi náà ti dahoro, ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì gẹ́gẹ́ bí aginjù; níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀; wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
11 In the withering of its branch it is broken off, Women are coming in [and] setting it on fire, For it [is] not a people of understanding, Therefore its Maker does not pity it, And its Former does not favor it.
Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́, nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn; bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
12 And it has come to pass in that day, YHWH beats out from the branch of the river, To the stream of Egypt, And you are gathered one by one, O sons of Israel.
Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
13 And it has come to pass in that day, It is blown with a great horn, And those perishing in the land of Asshur have come in, And those cast out in the land of Egypt, And have bowed themselves to YHWH, In the holy mountain—in Jerusalem!
Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.