< Genesis 46 >

1 And Israel journeys, and all that he has, and comes to Beer-Sheba, and sacrifices sacrifices to the God of his father Isaac;
Báyìí ni Israẹli mú ìrìnàjò rẹ̀ pọ̀n pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ní, nígbà tí ó sì dé Beerṣeba, ó rú ẹbọ sí Ọlọ́run Isaaki baba rẹ̀.
2 and God speaks to Israel in visions of the night and says, “Jacob, Jacob”; and he says, “Here I [am].”
Ọlọ́run sì bá Israẹli sọ̀rọ̀ ní ojú ìran ní òru pé, “Jakọbu! Jakọbu!” Ó sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
3 And He says, “I [am] God, God of your father, do not be afraid of going down to Egypt, for I set you there for a great nation;
Ọlọ́run sì wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run, Ọlọ́run baba rẹ, má ṣe bẹ̀rù láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti nítorí, èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá níbẹ̀.
4 I go down with you to Egypt, and I also certainly bring you up, and Joseph puts his hand on your eyes.”
Èmi yóò sì sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ lọ sí Ejibiti, èmi yóò sì tún mú ọ padà wá. Ọwọ́ Josẹfu fúnra rẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí.”
5 And Jacob rises from Beer-Sheba, and the sons of Israel carry away their father Jacob, and their infants, and their wives, in the wagons which Pharaoh has sent to carry him,
Nígbà náà ni Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, àwọn ọmọ Israẹli sì mú Jakọbu baba wọn àti àwọn aya wọn àti àwọn ọmọ wọn, wọ́n sì kó wọn sí inú kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Farao fi ránṣẹ́ fún ìrìnàjò rẹ̀.
6 and they take their livestock, and their goods which they have acquired in the land of Canaan, and come into Egypt—Jacob, and all his seed with him,
Wọ́n tún kó àwọn ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo ohun ìní tí wọ́n ti ní láti ilẹ̀ Kenaani, Jakọbu àti gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
7 his sons, and his sons’ sons with him, his daughters, and his sons’ daughters, indeed, all his seed he brought with him into Egypt.
Ó kó àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin pẹ̀lú àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ obìnrin, gbogbo irú-ọmọ rẹ̀ lọ sí Ejibiti.
8 And these [are] the names of the sons of Israel who are coming into Egypt: Jacob and his sons, Jacob’s firstborn, Reuben.
Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ Israẹli (Jakọbu àti ìran rẹ̀) tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ Ejibiti: Reubeni àkọ́bí Jakọbu.
9 And sons of Reuben: Enoch, and Phallu, and Hezron, and Carmi.
Àwọn ọmọkùnrin Reubeni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.
10 And sons of Simeon: Jemuel, and Jamin, and Ohad, and Jachin, and Zohar, and Shaul son of the Canaanite.
Àwọn ọmọkùnrin Simeoni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu, tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọbìnrin ará Kenaani.
11 And sons of Levi: Gershon, Kohath, and Merari.
Àwọn ọmọkùnrin Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
12 And sons of Judah: Er, and Onan, and Shelah, and Perez, and Zerah (and Er and Onan die in the land of Canaan). And sons of Perez are Hezron and Hamul.
Àwọn ọmọkùnrin Juda: Eri, Onani, Ṣela, Peresi àti Sera (ṣùgbọ́n Ẹri àti Onani ti kú ní ilẹ̀ Kenaani). Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
13 And sons of Issachar: Tola, and Phuvah, and Job, and Shimron.
Àwọn ọmọkùnrin: Isakari! Tola, Pua, Jaṣibu àti Ṣimroni.
14 And sons of Zebulun: Sered, and Elon, and Jahleel.
Àwọn ọmọkùnrin Sebuluni: Seredi, Eloni àti Jahaleli.
15 These [are] sons of Leah whom she bore to Jacob in Padan-Aram, and his daughter Dinah; all the persons of his sons and his daughters [are] thirty-three.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Lea tí ó bí fún Jakọbu ní Padani-Aramu yàtọ̀ fún Dina ọmọbìnrin rẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọ̀nyí jẹ́ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lápapọ̀.
16 And sons of Gad: Ziphion, and Haggi, Shuni, and Ezbon, Eri, and Arodi, and Areli.
Àwọn ọmọkùnrin Gadi: Sefoni, Haggi, Ṣuni, Esboni, Eri, Arodi, àti Areli.
17 And sons of Asher: Jimnah, and Ishuah, and Isui, and Beriah, and their sister Serah. And sons of Beriah: Heber and Malchiel.
Àwọn ọmọkùnrin Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn ni Sera. Àwọn ọmọkùnrin Beriah: Heberi àti Malkieli.
18 These [are] sons of Zilpah, whom Laban gave to his daughter Leah, and she bears these to Jacob—sixteen persons.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Jakọbu bí nípasẹ̀ Silipa, ẹni tí Labani fi fún Lea ọmọbìnrin rẹ̀. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́rìndínlógún lápapọ̀.
19 Sons of Rachel, Jacob’s wife: Joseph and Benjamin.
Àwọn ọmọkùnrin Rakeli aya Jakọbu: Josẹfu àti Benjamini.
20 And born to Joseph in the land of Egypt (whom Asenath daughter of Poti-Pherah, priest of On, has borne to him) [are] Manasseh and Ephraim.
Ní Ejibiti, Asenati ọmọbìnrin Potifẹra, alábojútó àti àlùfáà Oni, bí Manase àti Efraimu fún Josẹfu.
21 And sons of Benjamin: Belah, and Becher, and Ashbel, Gera, and Naaman, Ehi, and Rosh, Muppim, and Huppim, and Ard.
Àwọn ọmọ Benjamini: Bela, Bekeri, Aṣbeli, Gera, Naamani, Ehi, Roṣi, Mupimu, Huppimu àti Ardi.
22 These [are] sons of Rachel, who were born to Jacob; all the persons [are] fourteen.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rakeli bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá lápapọ̀.
23 And sons of Dan: Hushim.
Àwọn ọmọ Dani: Huṣimu.
24 And sons of Naphtali: Jahzeel, and Guni, and Jezer, and Shillem.
Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri, àti Ṣillemu.
25 These [are] sons of Bilhah, whom Laban gave to his daughter Rachel; and she bears these to Jacob—all the persons [are] seven.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Biliha ẹni tí Labani fi fún Rakeli ọmọ rẹ̀ bí fún Jakọbu. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.
26 All the persons who are coming to Jacob to Egypt, coming out of his thigh, apart from the wives of Jacob’s sons, all the persons [are] sixty-six.
Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jakọbu sí Ejibiti, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láìka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndínláàádọ́rin.
27 And the sons of Joseph who have been born to him in Egypt [are] two persons. All the persons of the house of Jacob who are coming into Egypt [are] seventy.
Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Josẹfu ní Ejibiti àwọn ará ilé Jakọbu tí ó lọ sí Ejibiti jẹ́ àádọ́rin lápapọ̀.
28 And Judah he has sent before him to Joseph, to direct before him to Goshen, and they come into the land of Goshen;
Jakọbu sì rán Juda ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Josẹfu, kí wọn bá à le mọ ọ̀nà Goṣeni. Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Goṣeni,
29 and Joseph harnesses his chariot, and goes up to meet his father Israel, to Goshen, and appears to him, and falls on his neck, and weeps on his neck again;
Josẹfu tọ́jú kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì lọ sí Goṣeni láti pàdé Israẹli baba rẹ̀. Bí Josẹfu ti dé iwájú baba rẹ̀, ó dì mọ́ baba rẹ̀ ó sì sọkún fún ìgbà pípẹ́.
30 and Israel says to Joseph, “Let me die this time, after my seeing your face, for you [are] yet alive.”
Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Wàyí o, mo le kú, níwọ̀n bí mo ti rí i fún ara mi pé, o wà láààyè síbẹ̀.”
31 And Joseph says to his brothers, and to the house of his father, “I go up, and declare to Pharaoh, and say to him, My brothers, and the house of my father who [are] in the land of Canaan have come to me;
Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ àti fún àwọn ará ilé baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò gòkè lọ, èmi yóò sì bá Farao sọ̀rọ̀, èmi yóò sì wí fún un pé, ‘Àwọn arákùnrin mi àti ìdílé baba mi tí ń gbé ní Kenaani ti tọ̀ mí wá.
32 and the men [are] feeders of a flock, for they have been men of livestock; and their flock, and their herd, and all that they have, they have brought.
Darandaran ni àwọn ènìyàn náà, wọ́n ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn, wọ́n sì kó agbo ẹran wọn àti agbo màlúù wọn àti gbogbo ohun tí wọ́n ní pẹ̀lú wá.’
33 And it has come to pass, when Pharaoh calls for you and has said, What [are] your works?
Nígbà tí Farao bá pè yín wọlé tí ó sí béèrè irú iṣẹ́ tí ẹ ń ṣe,
34 That you have said, Your servants have been men of livestock from our youth, even until now, both we and our fathers, in order that you may dwell in the land of Goshen, for the abomination of the Egyptians is everyone feeding a flock.”
ẹ fún un lésì pé, ‘Àwọn ìránṣẹ́ rẹ ń tọ́jú ẹran ọ̀sìn ni láti ìgbà èwe wa wá gẹ́gẹ́ bí a ṣe ba a lọ́wọ́ àwọn baba wa.’ Nígbà náà ni wọn yóò fún un yín láààyè láti tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni, nítorí pé àwọn ará Ejibiti kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ darandaran.”

< Genesis 46 >