< Genesis 25 >
1 And Abraham adds and takes a wife, and her name [is] Keturah;
Abrahamu sì tún fẹ́ aya mìíràn, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ketura.
2 and she bears to him Zimran, and Jokshan, and Medan, and Midian, and Ishbak, and Shuah.
Ó sì bí Simrani, Jokṣani, Medani, Midiani, Iṣbaki, àti Ṣua
3 And Jokshan has begotten Sheba and Dedan; and the sons of Dedan were Asshurim, and Letushim, and Leummim;
Jokṣani ni baba Ṣeba àti Dedani, àwọn ìran Dedani ni àwọn ara Asṣuri, Letusi àti Leumiti.
4 and the sons of Midian [are] Ephah, and Epher, and Enoch, and Abidah, and Eldaah: all these [are] sons of Keturah.
Àwọn ọmọ Midiani ni Efani, Eferi, Hanoku, Abida àti Eldaa. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Ketura.
5 And Abraham gives all that he has to Isaac;
Abrahamu sì fi ohun gbogbo tí ó ní fún Isaaki.
6 and to the sons of the concubines whom Abraham has, Abraham has given gifts, and sends them away from his son Isaac (in his being yet alive) eastward, to the east country.
Ṣùgbọ́n kí Abrahamu tó kú, Abrahamu fún àwọn ọmọ tí àwọn àlè rẹ̀ bí fún un ní ẹ̀bùn, ó sì lé wọn jáde lọ fún Isaaki ọmọ rẹ sí ilẹ̀ ìlà-oòrùn.
7 And these [are] the days of the years of the life of Abraham, which he lived, one hundred and seventy-five years;
Gbogbo àpapọ̀ ọdún tí Abrahamu lò láyé jẹ́ igba kan ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
8 and Abraham expires, and dies in a good old age, aged and satisfied, and is gathered to his people.
Abrahamu sì kú ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ó dàgbà, ó darúgbó kí ó tó kú. A sì sin ín sí ibojì àwọn ènìyàn rẹ̀.
9 And his sons Isaac and Ishmael bury him at the cave of Machpelah, at the field of Ephron, son of Zoar the Hittite, which [is] before Mamre—
Àwọn ọmọ rẹ̀, Isaaki àti Iṣmaeli sì sin ín sínú ihò àpáta ni Makpela ní ẹ̀gbẹ́ Mamre, ní oko Efroni ọmọ Sohari ará Hiti,
10 the field which Abraham bought from the sons of Heth—there Abraham has been buried, and his wife Sarah.
inú oko tí Abrahamu rà lọ́wọ́ ara Hiti yìí ni a sin Abrahamu àti Sara aya rẹ̀ sí.
11 And it comes to pass after the death of Abraham, that God blesses his son Isaac; and Isaac dwells by the Well of the Living One, my Beholder.
Lẹ́yìn ikú Abrahamu, Ọlọ́run sì bùkún fún Isaaki ọmọ rẹ̀, tí ó ń gbé nítòsí kànga Lahai-Roi ní ìgbà náà.
12 And these [are] the generations of Ishmael, Abraham’s son, whom Hagar the Egyptian, Sarah’s handmaid, has borne to Abraham;
Wọ̀nyí ni ìran Iṣmaeli, ọmọ Abrahamu ẹni tí Hagari ará Ejibiti, ọmọ ọ̀dọ̀ Sara bí fún un.
13 and these [are] the names of the sons of Ishmael, by their names, according to their births: firstborn of Ishmael, Nebajoth; and Kedar, and Adbeel, and Mibsam,
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli bí a ṣe bí wọn, bẹ̀rẹ̀ láti orí: Nebaioti àkọ́bí, Kedari, Adbeeli, Mibsamu,
14 and Mishma, and Dumah, and Massa,
Miṣima, Duma, Massa,
15 Hadar, and Tema, Jetur, Naphish, and Kedemah:
Hadadi, Tema, Jeturi, Nafiṣi, àti Kedema.
16 these are sons of Ishmael, and these [are] their names, by their villages, and by their towers; twelve princes according to their peoples.
Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli, wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọba méjìlá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn.
17 And these [are] the years of the life of Ishmael, one hundred and thirty-seven years; and he expires, and dies, and is gathered to his people;
Àpapọ̀ ọdún tí Iṣmaeli lò láyé jẹ́ ẹ̀tàdínlógóje ọdún, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
18 and they dwell from Havilah to Shur, which [is] before Egypt, in [your] going toward Asshur; in the presence of all his brothers has he fallen.
Àwọn ìran rẹ̀ sì tẹ̀dó sí agbègbè Hafila títí tí ó fi dé Ṣuri, ní ẹ̀bá ààlà Ejibiti, bí ìwọ ti ń lọ sí ìhà Asiria. Ó sì kú níwájú àwọn arákùnrin rẹ̀ gbogbo.
19 And these [are] the generations of Isaac, Abraham’s son: Abraham has begotten Isaac;
Wọ̀nyí ni ìtàn ìran Isaaki ọmọ Abrahamu. Abrahamu bí Isaaki.
20 and Isaac is a son of forty years in his taking Rebekah, daughter of Bethuel the Aramean, from Padan-Aram, sister of Laban the Aramean, to him for a wife.
Nígbà tí Isaaki di ọmọ ogójì ọdún ni ó gbé Rebeka ọmọ Betueli ará Aramu ti Padani-Aramu tí í ṣe arábìnrin Labani ará Aramu ní ìyàwó.
21 And Isaac makes plea to YHWH before his wife, for she [is] barren: and YHWH accepts his plea, and his wife Rebekah conceives,
Isaaki sì gbàdúrà sì Olúwa, nítorí aya rẹ̀ tí ó yàgàn, Olúwa sì gbọ́ àdúrà rẹ̀, Rebeka sì lóyún.
22 and the children struggle together within her, and she says, “If [it is] right—why [am] I thus?” And she goes to seek YHWH.
Àwọn ọmọ náà ń gbún ara wọn nínú rẹ̀, ó sì wí pé, “Èéṣe tí èyí ń ṣẹlẹ̀ sí mi,” ó sì lọ béèrè lọ́dọ̀ Olúwa.
23 And YHWH says to her, “Two nations [are] in your womb, and two peoples from your bowels are parted; and the [one] people is stronger than the [other] people; and the older serves the younger.”
Olúwa sì wí fún un pé, “Orílẹ̀-èdè méjì ni ń bẹ nínú rẹ, irú ènìyàn méjì ni yóò yà láti inú rẹ; àwọn ènìyàn kan yóò jẹ́ alágbára ju èkejì lọ, ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
24 And her days to bear are fulfilled, and behold, twins [are] in her womb;
Nígbà tí ó tó àkókò fún un láti bímọ, ìbejì ni ó wà nínú rẹ̀, ọkùnrin sì ni wọ́n.
25 and the first comes out all red as a hairy robe, and they call his name Esau;
Èyí tí ó kọ jáde jẹ́ ọmọ pupa, irun sì bo gbogbo ara rẹ̀ bí aṣọ onírun, nítorí náà, wọ́n pè é ní Esau.
26 and afterward his brother has come out, and his hand is taking hold on Esau’s heel, and one calls his name Jacob; and Isaac [is] a son of sixty years in her bearing them.
Lẹ́yìn èyí ni arákùnrin èkejì jáde wá, ọwọ́ rẹ̀ sì di Esau ni gìgísẹ̀ mú, nítorí náà ni wọn ṣe pe orúkọ rẹ ni Jakọbu. Ọmọ ọgọ́ta ọdún ni Isaaki, nígbà tí Rebeka bí wọn.
27 And the youths grew, and Esau is a man acquainted [with] hunting, a man of the field; and Jacob [is] a plain man, inhabiting tents;
Àwọn ọmọkùnrin náà sì dàgbà. Esau sì di ọlọ́gbọ́n ọdẹ, ẹni tí ó fẹ́ràn àti máa dúró ní oko. Jakọbu sì jẹ́ ènìyàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń gbé láàrín ìlú.
28 and Isaac loves Esau, for [his] game [is] in his mouth; and Rebekah is loving Jacob.
Isaaki, ẹni tí ó fẹ́ràn ẹran igbó fẹ́ràn Esau nítorí ẹran igbó tí Esau máa ń pa, ṣùgbọ́n Rebeka fẹ́ràn Jakọbu.
29 And Jacob boils stew, and Esau comes in from the field, and he [is] weary;
Ní ọjọ́ kan, Jakọbu sì pa ìpẹ̀tẹ̀, Esau sì ti igbó ọdẹ dé, ó sì ti rẹ̀ ẹ́.
30 and Esau says to Jacob, “Please let me eat some of this red-red thing, for I [am] weary”; therefore [one] has called his name Edom;
Esau wí fún Jakọbu pé, “Èmí bẹ̀ ọ, fi ìpẹ̀tẹ̀ rẹ pupa n nì bọ́ mi, nítorí tí ó rẹ̀ mí gidigidi.” (Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ rẹ̀ ní Edomu.)
31 and Jacob says, “Sell your birthright to me today.”
Jakọbu dáhùn pé, “Kò burú, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ta ogún ìbí rẹ fún mi ná.”
32 And Esau says, “Behold, I am going to die, and what is this to me—a birthright?”
Esau sì dáhùn pé, “Wò ó mo ti fẹ́rẹ kú, àǹfààní kín sì ni ogún ìbí jẹ́ fún mi?”
33 And Jacob says, “Swear to me today”: and he swears to him, and sells his birthright to Jacob;
Ṣùgbọ́n, Jakọbu dáhùn pé, “Kọ́kọ́ búra fún mi pé tèmi ni ogún ìbí náà yóò jẹ́.” Báyìí ni Esau búra tí ó sì gbé ogún ìbí rẹ̀ tà fún Jakọbu.
34 and Jacob has given bread and stew of lentils to Esau, and he eats, and drinks, and rises, and goes; and Esau despises the birthright.
Nígbà náà ni Jakọbu fi àkàrà àti ìpẹ̀tẹ̀ lẹntili fún Esau. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì bá tirẹ̀ lọ. Báyìí ni Esau gan ogún ìbí rẹ̀.