< Esther 8 >
1 On that day has King Ahasuerus given to Esther the queen the house of Haman, adversary of the Jews, and Mordecai has come in before the king, for Esther has declared what he [is] to her,
Ní ọjọ́ kan náà ni ọba Ahaswerusi fún Esteri ayaba ní ilé e Hamani, ọ̀tá àwọn Júù. Mordekai sì wá síwájú ọba, nítorí Esteri ti sọ bí ó ṣe jẹ́ sí ọba.
2 and the king turns aside his signet, that he has caused to pass away from Haman, and gives it to Mordecai, and Esther sets Mordecai over the house of Haman.
Ọba sì bọ́ òrùka dídán an rẹ̀, èyí tí ó ti gbà lọ́wọ́ Hamani ó sì fi fún Mordekai, Esteri sì yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí ilé e Hamani.
3 And Esther adds, and speaks before the king, and falls before his feet, and weeps, and makes supplication to him, to cause the evil of Haman the Agagite to pass away, and his scheme that he had devised against the Jews;
Esteri sì tún bẹ ọba lórí ìkúnlẹ̀, pẹ̀lú omijé lójú. Ó bẹ̀ ẹ́ kí ó fi òpin sí ètò búburú Hamani ará Agagi, èyí tí ó ti pète fún àwọn Júù.
4 and the king holds out to Esther the golden scepter, and Esther rises, and stands before the king,
Nígbà náà ni ọba na ọ̀pá aládé wúrà sí Esteri ó sì dìde, ó dúró níwájú rẹ̀.
5 and says, “If to the king [it be] good, and if I have found grace before him, and the thing has been right before the king, and I [am] good in his eyes, let it be written to bring back the letters—a scheme of Haman son of Hammedatha the Agagite—that he wrote to destroy the Jews who [are] in all provinces of the king,
Ó wí pé, “Bí ó bá wu ọba, tí ó bá sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ojúrere tí ó sì rò pé ohun tí ó dára ni láti ṣe, tí ó bá sì ní inú dídùn pẹ̀lú mi, jẹ́ kí a kọ ìwé àṣẹ láti yí ète tí Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, tí ó kọ́ pàṣẹ pé kí a pa àwọn Júù tí wọ́n wà ní gbogbo àgbáyé ìjọba ọba run.
6 for how do I endure when I have looked on the evil that finds my people? And how do I endure when I have looked on the destruction of my family?”
Nítorí báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á tí èmi yóò sì rí kí ibi máa ṣubú lu àwọn ènìyàn mi? Báwo ni èmi yóò ṣe fi ara dà á, tí èmi yóò sì máa wo ìparun àwọn ìdílé mi?”
7 And King Ahasuerus says to Esther the queen, and to Mordecai the Jew, “Behold, the house of Haman I have given to Esther, and him they have hanged on the tree, because that he put forth his hand on the Jews,
Ọba Ahaswerusi dá Esteri ayaba àti Mordekai ará a Júù náà lóhùn pé, “Nítorí Hamani kọlu àwọn ará a Júù, èmi ti fi ilé e rẹ̀ fún Esteri, wọ́n sì ti ṣo ó kọ́ sórí igi.
8 and you, write for the Jews, as [it is] good in your eyes, in the name of the king, and seal with the signet of the king—for the writing that is written in the name of the king, and sealed with the signet of the king, there is none to turn back.”
Nísinsin yìí, kọ ìwé àṣẹ mìíràn ní orúkọ ọba bí àwọn Júù ṣe jẹ́ pàtàkì sí ọ, kí o sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì dì í, nítorí kò sí àkọsílẹ̀ tí a bá ti kọ ní orúkọ ọba tí a sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì tí a lè yìí padà.”
9 And the scribes of the king are called, at that time, in the third month—it [is] the month of Sivan—in the twenty-third [day] of it, and it is written, according to all that Mordecai has commanded, to the Jews, and to the lieutenants, and the governors, and the heads of the provinces, that [are] from Hodu even to Cush, one hundred twenty-seven provinces—province and province according to its writing, and people and people according to its tongue, and to the Jews according to their writing, and according to their tongue.
Lẹ́sẹ̀kan náà àwọn akọ̀wé ọba péjọ ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kẹta, oṣù Sifani. Wọ́n kọ gbogbo àṣẹ Mordekai sí àwọn Júù, àti sí àwọn alákòóso baálẹ̀ àti àwọn ọlọ́lá ìgbèríko mẹ́tàdínláàádóje tí ó lọ láti India títí ó fi dé Kuṣi. Kí a kọ àṣẹ náà ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé àti bí èdè olúkúlùkù àti pẹ̀lú sí àwọn Júù ní ìlànà bí wọ́n ṣe ń kọ̀wé àti èdè e wọn.
10 And he writes in the name of King Ahasuerus, and seals with the signet of the king, and sends letters by the hand of the runners with horses, riders of the dromedary, the mules, the young mares,
Mordekai sì fi àṣẹ ọba Ahaswerusi kọ̀wé, ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀, ó rán an lọ ní kíákíá, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ ayaba, tiwọn yára bí àṣà àwọn tí wọ́n ń gun ẹṣin tí ó yára, ní pàtàkì èyí tí a ń bọ́ fún ọba.
11 that the king has given to the Jews who [are] in each and every city, to be assembled, and to stand for their life, to cut off, to slay, and to destroy the whole force of the people and province who are distressing them, infants and women, and their spoil to seize.
Àṣẹ ọba sì dé ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní gbogbo ìlú láti kó ara wọn jọ kí wọn sì dáàbò bo ara wọn; láti pa, láti run àti láti kọlu ogunkógun orílẹ̀-èdè kórílẹ̀ èdè kankan tàbí ìgbèríko tí ó bá fẹ́ kọlù wọ́n, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn; kí ẹ sì kó gbogbo ohun ìní àwọn ọ̀tá wọn.
12 In one day, in all the provinces of King Ahasuerus, on the thirteenth of the twelfth month—it [is] the month of Adar—
Ọjọ́ tí a yàn fún àwọn Júù ní gbogbo agbègbè ọba Ahaswerusi láti ṣe nǹkan yìí ni ọjọ́ kẹtàlá èyí tí í ṣe oṣù kejìlá, oṣù Addari.
13 a copy of the writing to be made law in each and every province is revealed to all the peoples, and for the Jews being ready at this day to be avenged of their enemies.
Ọkàn ìwé àṣẹ náà ni kí a gbé jáde gẹ́gẹ́ bí òfin ní gbogbo ìgbèríko kí ẹ sì jẹ́ kí ó di mí mọ̀ fún gbogbo ènìyàn ìlú nítorí àwọn Júù yóò le è múra ní ọjọ́ náà láti gbẹ̀san fún ara wọn lára àwọn ọ̀tá wọn.
14 The runners, riding on the dromedary, [and] the mules, have gone out, hurried and pressed by the word of the king, and the law has been given in Shushan the palace.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ ayaba tiwọn yára bí àṣà tí wọ́n ń gun ẹṣin ọba, sáré jáde, wọ́n sáré lọ nípa àṣẹ ọba. A sì tún gbé àṣẹ náà jáde ní ilé ìṣọ́ ti Susa.
15 And Mordecai went out from before the king, in royal clothing of blue and white, and a great crown of gold, and a garment of fine linen and purple, and the city of Shushan has rejoiced and been glad;
Mordekai sì kúrò níwájú ọba, ó wọ aṣọ aláró àti funfun, ó dé adé e wúrà ńlá pẹ̀lú ìgbànú elése àlùkò dáradára, ìlú Susa sì ṣe àjọyọ̀ ńlá.
16 to the Jews has been light, and gladness, and joy, and honor,
Àsìkò ìdùnnú àti ayọ̀, inú dídùn àti ọlá ni ó jẹ́ fún àwọn Júù.
17 and in each and every province, and in each and every city, the place where the word of the king, even his law, is coming, gladness and joy [are] to the Jews, a banquet, and a good day; and many of the peoples of the land are becoming Jews, for a fear of the Jews has fallen on them.
Ní gbogbo ìgbèríko àti ní gbogbo ìlú, ní gbogbo ibi tí àṣẹ ọba dé, ni ayọ̀ àti inú dídùn ti wà láàrín àwọn Júù, wọ́n sì ń ṣe àsè àti àjọyọ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tókù sọ ara wọn di Júù nítorí ẹ̀rù àwọn Júù bà wọ́n.