< Psalms 91 >

1 He who sitteth under the secret protection of the Most High, shall rest under the shadow of the Almighty.
Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
2 I will say of the Lord, who is my refuge and my stronghold, my God, in whom I ever trust,
Èmi yóò sọ nípa ti Olúwa pé, “Òun ni ààbò àti odi mi, Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
3 That he will surely deliver thee from the snare of the fowler, and from the pestilence of destruction.
Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
4 With his pinions will he cover thee, and under his wings shalt thou find shelter: shield and buckler is his truth.
Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí, àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
5 Thou shalt not be afraid of the terror of the night; nor of the arrow that flieth by day;
Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru, tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
6 Nor of the pestilence that stalketh in darkness; nor of the deadly disease that wasteth at noonday.
tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn, tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
7 There shall fall at thy side a thousand, and ten thousand at thy right hand; unto thee [however] shall it not come nigh.
Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
8 Only with thy eyes shalt thou behold it, and see the recompense of the wicked.
Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
9 Because thou hast [said], The Lord is my protection, the Most High hast thou made thy refuge:
Nítorí ìwọ fi Olúwa ṣe ààbò rẹ, ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
10 No evil shall befall thee, nor shall any plague come nigh unto thy tent.
Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́, Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
11 For his angels will he give charge concerning thee, to guard thee on all thy ways.
Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
12 Upon [their] hands shall they bear thee, that thou mayest not dash against a stone thy foot.
wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn, nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
13 Upon the fierce lion and asp shalt thou tread: thou shalt trample under foot the young lion and serpent.
Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀; ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
14 Because he hath fixed his desire upon me, therefore will I release him: I will set him on high, because he knoweth my name.
“Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́; èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
15 He will call on me, and I will answer him: with him will I be in distress; I will deliver him, and grant him honor.
Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn; èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú, èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
16 With length of days will I satisfy him, and I will let him see my salvation.
Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn, èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”

< Psalms 91 >