< Psalms 33 >
1 Be joyful, O ye righteous, in the Lord; [for] unto the righteous praise is comely.
Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
2 Give thanks unto the Lord with the harp: with the ten-stringed psaltery do ye sing [praises] unto him.
Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
3 Sing unto him a new song; play beautifully amidst a triumphant shout.
Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
4 For the word of the Lord is upright; and all his works [are done] in truth.
Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
5 He loveth righteousness and justice: the earth is full of the kindness of the Lord.
Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
6 By the word of the Lord were the heavens made; and by the breath of his mouth all their host.
Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
7 He gathereth together like heaps the waters of the sea: he layeth up in store-houses the depths [of the sea].
Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
8 Let all the earth fear the Lord: of him stand in awe all the inhabitants of the world.
Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
9 For he spoke, and it came into being: he commanded, and it stood fast.
Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
10 The Lord frustrateth the resolves of the nations: he bringeth to nought the thoughts of the people.
Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
11 The counsel of the Lord will stand for ever, the thoughts of his heart from generation to generation.
Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
12 Happy is the nation whose God is the Lord, the people whom he hath chosen for himself as a heritage.
Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
13 The Lord looketh from heaven; he seeth all the sons of men.
Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
14 From the place of his habitation he directeth his view upon all the inhabitants of the earth;
Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
15 He fashioneth their hearts altogether; he hath regard to all their works.
ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
16 The king is not saved by the multitude of an army: a mighty man is not delivered by much strength.
A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
17 Vain is the horse for victory: nor shall he deliver any by the greatness of his strength.
Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
18 Behold, the eye of the Lord is upon those that fear him, upon those that hope for his kindness.
Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
19 To deliver from death their soul, and to keep them alive in famine.
Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
20 Our soul waiteth for the Lord: our help and our shield is he.
Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
21 For in him shall our heart rejoice: because in his holy name have we trusted.
Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
22 Let thy kindness, O Lord, be upon us, even as we hope in thee.
Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.