< Psalms 116 >

1 It is lovely to me that the Lord heareth my voice, my supplications.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 For he hath inclined his ear unto me: therefore throughout all my days will I call on him.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 The bands of death had compassed me, and the pangs of the nether world had overtaken me; I had met with distress and sorrow: (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 I then called on the name of the Lord, I beseech thee, O Lord, release my soul.
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 Gracious is the Lord, and righteous; and our God is merciful.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 The Lord preserveth the simple: I was in misery, and he helped me.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Return, O my soul, unto thy rest; for the Lord hath dealt bountifully with thee.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 For thou hast delivered my soul from death, my eyes from tears, my feet from falling.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 I will walk before the Lord in the land of life.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 I believe, therefore will I speak: I was greatly afflicted;
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 I indeed said in my despondency, Every man is a liar.
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 What shall I give in return unto the Lord for all his bounties toward me?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 The cup of salvation will I lift up, and on the name of the Lord will I call.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 My vows will I pay unto the Lord, yea, in the presence of all his people.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Grievous in the eyes of the Lord is the death of his pious ones.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 O Lord, truly am I thy servant, I am thy servant, —the son of thy handmaid: thou hast loosened my fetters.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 Unto thee will I offer the sacrifice of thanksgiving, and on the name of the Lord will I call.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 My vows will I pay unto the Lord, yea, in the presence of all his people,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 In the courts of the house of the Lord, in thy midst, O Jerusalem. Hallelujah.
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Psalms 116 >