< Proverbs 27 >
1 Make no boast for thyself of the coming day; for thou knowest not what a day may bring forth.
Má ṣe yangàn nítorí ọ̀la nítorí o kò mọ ohun tí ọjọ́ kan le è mú wáyé.
2 Let another man praise thee, and not thy own mouth; a stranger, and not thy own lips.
Jẹ́ kí ẹlòmíràn yìn ọ́ dípò ẹnu ara rẹ, àní àlejò, kí ó má sì ṣe ètè ìwọ fúnra rẹ̀.
3 A stone hath heaviness, and the sand, weight; but a fool's wrath is heavier than both of them.
Òkúta wúwo, erùpẹ̀ sì wúwo ṣùgbọ́n ìbínú aṣiwèrè wúwo ju méjèèjì lọ.
4 Fury hath its cruelty, and anger its overwhelming power; but who is able to stand before jealousy?
Ìbínú ni ìkà, ìrunú sì burú púpọ̀ ṣùgbọ́n ta ni ó le è dúró níwájú owú?
5 Better is open reproof than concealed love.
Ìbániwí gbangba sàn ju ìfẹ́ ìkọ̀kọ̀ lọ.
6 Faithful are the wounds of a friend; but deceptive are the kisses of an enemy.
Òtítọ́ ni ọgbẹ́ ọ̀rẹ́, ṣùgbọ́n ìfẹnukonu ọ̀tá ni ẹ̀tàn.
7 The satisfied soul treadeth under foot fine honey; but to the hungry soul every bitter thing is sweet.
Kódà oyin kò dùn lẹ́nu ẹni tí ó ti yó ṣùgbọ́n òróǹró gan an dùn lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.
8 As a bird that wandereth away from her nest, so is a man that wandereth away from his place.
Bí ẹyẹ tí ó ṣáko lọ kúrò níbi ìtẹ́ rẹ̀ ni ènìyàn tí ó ṣáko lọ kúrò ní ilé rẹ̀.
9 Oil and perfume cause the heart to rejoice, and so do the sweet words of a friend more than one's own counsel.
Ìpara olóòórùn dídùn àti tùràrí ń mú ayọ̀ wá sínú ọkàn bẹ́ẹ̀ ni inú dídùn láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ ń wá láti inú ìmọ̀ràn tí ó ṣàkóso.
10 Thy own friend, and thy father's friend, thou must not forsake; but into thy brother's house enter not on the day of thy calamity: better is a near neighbor than a distant brother.
Má ṣe kọ ọ̀rẹ́ rẹ àti ọ̀rẹ́ baba rẹ sílẹ̀, má sì ṣe lọ sílé arákùnrin rẹ nígbà tí ìdààmú dé bá ọ ó sàn kí o jẹ́ aládùúgbò tí ó súnmọ́ ni ju arákùnrin tí ó jìnnà sí ni.
11 Become wise, my son, and cause my heart to rejoice, that I may give an answer to him that reproacheth me.
Gbọ́n, ọmọ mi, kí o sì mú ayọ̀ wá sínú ọkàn mi nígbà náà ni mo le dá gbogbo ẹni tí ó bá kẹ́gàn mi.
12 The prudent foreseeth the evil, and hideth himself; but the simple pass on, and are punished.
Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fi ara pamọ́ ṣùgbọ́n aláìgbọ́n rí, kàkà kí ó dúró ó tẹ̀síwájú, ó sì jìyà rẹ̀.
13 Take his garment, for he became surety for a stranger; and on account of an alien woman take a pledge of him.
Gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àjèjì fi ṣe ẹ̀rí ìdúró bí o bá ṣe onídùúró fún obìnrin oníṣekúṣe.
14 When one saluteth his friend with a loud voice, when rising early in the morning, it will be counted a curse to him.
Bí ènìyàn kan ń kígbe súre fún aládùúgbò rẹ ní òwúrọ̀ a ó kà á sí bí èpè.
15 A continual dropping on a very rainy day and a contentious woman are alike.
Àyà tí ó máa ń jà dàbí ọ̀wààrà òjò ní ọjọ́ tí òjò ń rọ̀;
16 He that would conceal her might conceal the wind, and as [fragrant] oil on his right hand, which would betray itself.
dídá a lẹ́kun dàbí ìgbà tí ènìyàn ń dá afẹ́fẹ́ lẹ́kun tàbí bí ẹni tí ó gbá òróró.
17 Iron is sharpened by iron: so doth a man sharpen himself on the countenance of his friend.
Bí irin tí ń pọ́n irin mú bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn kan ń pọ́n ẹlòmíràn mú.
18 Whoso guardeth the fig-tree will eat its fruit: so he that watcheth over his master will be honored.
Ẹni tí ó tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóò jẹ èso rẹ̀ ẹni tí ó sì fojú tó ọ̀gá rẹ̀ yóò gba ọlá.
19 As the water [showeth] to the face the [reflected] face: so doth the heart of man show itself to man.
Bí omi tí ń ṣe àfihàn ojú, nígbà tí a bá wò ó bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ènìyàn ń ṣe àfihàn ènìyàn.
20 The nether world and the place of corruption are never satisfied: so are the eyes of man never satisfied. (Sheol )
Kò tẹ́ ikú àti ìparun lọ́rùn rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ojú ènìyàn kò rí ìtẹ́lọ́rùn rí. (Sheol )
21 [As] the fining-pot is for silver, and the furnace for gold: so is a man [proved] according to his praise.
Iná fún fàdákà iná ìléru fún wúrà, ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.
22 Though thou shouldst pound the fool in a mortar, in the midst of grains of wheat with a pestle: still would his folly not depart from him.
Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó, fi ọmọ odó gún un bí èlùbọ́ ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.
23 Endeavor to know well the appearance of thy flocks, direct thy attention to thy herds;
Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wà bojútó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;
24 For property endureth not for ever, nor doth the crown remain for all generations.
nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí adé kì í sì í wà lórí títí láéláé.
25 When the grass is past, young verdure showeth itself, and then are gathered the herbs of the mountains.
Nígbà tí a bá kó koríko, ewéko tuntun yóò sì hù jáde, a ó sì kó koríko àwọn orí òkè wọlé
26 The sheep are for thy clothing, and he-goats are the purchase-price of a field.
àwọn àgùntàn yóò pèsè aṣọ fún ọ, àti ewúrẹ́ yóò pèsè owó oko.
27 And thou wilt have enough of goats' milk for thy food, for the food of thy household, and the support for thy maidens.
Ìwọ yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà ewúrẹ́ láti bọ́ ọ àti ìdílé rẹ àti láti tọ́jú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.