< Proverbs 1 >

1 The proverbs of Solomon the son of David, the king of Israel:
Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
2 To know wisdom and instruction; to comprehend the sayings of understanding;
Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́, láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.
3 To accept the instruction of intelligence, righteousness, and justice, and equity;
Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo, àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;
4 To give to the simple prudence, to the youth knowledge and discretion.
láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀, ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.
5 The wise will hear, and will increase [his] information; and the man of understanding will obtain wise counsels:
Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀, sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.
6 To understand a proverb, and a sage sentence; the words of the wise, and their riddles.
Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe, àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.
7 The fear of the Lord is the beginning of knowledge: wisdom and instruction fools [alone] despise.
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.
8 Hear, my son, the instruction of thy father, and cast not off the teaching of thy mother;
Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.
9 For a wreath of grace are they unto thy head, and chains for thy throat.
Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.
10 My son, if sinners wish to entice thee, consent thou not.
Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́, má ṣe gbà fún wọn.
11 If they should say, Come with us, let us lie in wait for blood, let us watch in concealment for the uselessly innocent;
Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa; jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan, jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;
12 We will swallow them up like the grave alive; and the men of integrity, as those that go down into the pit; (Sheol h7585)
jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú, àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò; (Sheol h7585)
13 We shall find all [kinds of] precious wealth, we will fill our houses with booty;
a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa,
14 Thy lot must thou cast in our midst; one purse shall be for us all:
da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa, a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà,”
15 My son, walk not thou on the way with them; withhold thy foot from their path;
ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ, má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn.
16 For their feet run after evil, and they make haste to shed blood.
Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀, wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
17 For uselessly is the net spread out before the eyes of every winged bird:
Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀, ní ojú ẹyẹ!
18 While they lie in wait for their [own] blood; they watch in concealment for their [own] lives.
Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn. Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà.
19 So are the paths of every one that is greedy after [unlawful] gain; it taketh away the life of those that own it.
Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́; yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.
20 Wisdom crieth loudly without; in the public places she uttereth her voice;
Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;
21 At the corner of noisy streets she calleth, at the entrances of gates; in the city she sayeth her speeches:
láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:
22 How long, ye simple ones, will ye love simplicity? and the scorners take their delight in scorning, and fools hate knowledge?
“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó? Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó? Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?
23 Turn back to my admonition: behold, I will pour out my spirit unto you, I will make known my words unto you.
Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni, ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.
24 Whereas I called, and ye refused; I stretched out my hand, and no man was attentive;
Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,
25 And ye have set at nought all my counsel, and would not accept my admonition:
níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi, tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,
26 [Therefore] I also will truly laugh at your calamity; I will deride [you] when your terror cometh;
Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín; èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.
27 When your terror cometh like the tempest-cloud, and your calamity hasteneth like a whirlwind; when there come upon you distress and affliction.
Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle, nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà, nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.
28 Then will they call me, but I will not answer; they will seek me earnestly, but they shall not find me;
“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn; wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.
29 For the reason that they hated knowledge, and the fear of the Lord they did not choose;
Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀ tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.
30 [That] they would not attend to my counsel: [that] they rejected all my admonition.
Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,
31 Therefore shall they eat of the fruit of their own way, and from their own counsels shall they be satisfied.
wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún.
32 For the defection of the simple will slay them, and the prosperity of fools will cause them to be lost.
Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;
33 But he that hearkeneth unto me shall dwell safely, and shall be at rest from the dread of evil.
ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

< Proverbs 1 >