< Numbers 1 >

1 And the Lord spoke unto Moses in the wilderness of Sinai, in the tabernacle of the congregation, on the first day of the second month, in the second year after their going out of the land of Egypt, saying,
Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
2 Take ye the sum of all the congregation of the children of Israel, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, every male according to their polls;
“Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
3 From twenty years old and upward, all that are able to go forth to war in Israel: these shall ye number according to their armies, thou and Aaron.
Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
4 And with you there shall be one man each of every tribe; a man who is the head of his family division.
Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
5 And these are the names of the men that shall stand with you; of Reuben: Elizur the son of Shedeur.
“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
6 Of Simeon: Shelumiel the son of Zurishaddai.
Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
7 Of Judah: Nachshon the son of 'Amminadab.
Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
8 Of Issachar: Nethanel the son of Zuar.
Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
9 Of Zebulun: Eliab the son of Chelon.
Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
10 Of the children of Joseph, of Ephraim: Elishama the son of 'Ammihud; of Menasseh: Gamliel the son of Pedahzur.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
11 Of Benjamin: Abidan the son of Gidoni.
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
12 Of Dan: Achiezer the son of 'Ammishaddai.
Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
13 Of Asher: Pagiel the son of 'Ochran.
Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
14 Of Gad: Elyassaph the son of Deuel.
Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
15 Of Naphtali: Achira the son of 'Enan.
Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
16 These were the selected of the congregation, the princes of the tribes of their fathers; the heads of the thousands of Israel were they.
Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
17 And Moses and Aaron took these men who are expressed by name:
Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
18 And all the congregation they assembled together on the first day of the second month, and they were enrolled in the lists of their pedigrees after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, according to their polls.
wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
19 As the Lord had commanded Moses, so did he number them in the wilderness of Sinai.
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
20 And there were of the children of Reuben the first-born of Israel, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names according to their polls, every male from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
21 Those that were numbered of the tribe of Reuben, were forty and six thousand and five hundred.
Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
22 Of the children of Simeon, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, those that were numbered of them, by numbering the names according to their polls, every male from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
23 Those that were numbered of the tribe of Simeon, were fifty and nine thousand and three hundred.
Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
24 Of the children of Gad, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
25 Those that were numbered of the tribe of Gad, were forty and five thousand six hundred and fifty.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
26 Of the children of Judah, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
27 Those that were numbered of the tribe of Judah, were seventy and four thousand and six hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
28 Of the children of Issachar, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
29 Those that were numbered of the tribe of Issachar, were fifty and four thousand and four hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
30 Of the children of Zebulun, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
31 Those that were numbered of the tribe of Zebulun, were fifty and seven thousand and four hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
32 Of the children of Joseph, namely, of the children of Ephraim, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war.
Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
33 Those that were numbered of the tribe of Ephraim, were forty thousand and five hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
34 Of the children of Menasseh, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
35 Those that were numbered of the tribe of Menasseh, were thirty and two thousand and two hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
36 Of the children of Benjamin, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
37 Those that were numbered of the tribe of Benjamin, were thirty and five thousand and four hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
38 Of the children of Dan, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
39 Those that were numbered of the tribe of Dan, were sixty and two thousand and seven hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
40 Of the children of Asher, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
41 Those that were numbered of the tribe of Asher, were forty and one thousand and five hundred.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
42 Of the children of Naphtali, by their generations, after their families, by the descent from their fathers, by numbering the names, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war;
Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
43 Those that were numbered of the tribe of Naphtali, were fifty and three thousand and four hundred.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
44 These are those that were numbered, whom Moses numbered with Aaron, and the princes of Israel, being twelve men; one man each for his family division were they.
Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
45 Thus were all those that were numbered of the children of Israel, by the descent from their fathers, from twenty years old and upward, all that were able to go forth to war in Israel, —
Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
46 Even all they that were numbered, were six hundred thousand and three thousand and five hundred and fifty.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
47 But the Levites, after the tribe of their fathers, were not numbered among them.
A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
48 For the Lord had spoken unto Moses, saying,
Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
49 Only the tribe of Levi shalt thou not number, and their sum shalt thou not take, among the children of Israel;
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
50 But thou shalt appoint the Levites over the tabernacle of the testimony, and over all its vessels, and over all things that belong to it: they shall carry the tabernacle, and all its vessels; and they shall minister unto it; and round about the tabernacle shall they encamp.
Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
51 And when the tabernacle is to be carried forward, the Levites shall take it down; and when the tabernacle is to be pitched, the Levites shall set it up: and the stranger that cometh nigh shall be put to death.
Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
52 And the children of Israel shall pitch their tents, every man by his own camp, and every man by his own standard, according to their armies.
kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
53 But the Levites shall encamp round shout the tabernacle of the testimony, that there be no wrath upon the congregation of the children of Israel: and the Levites shall keep the charge of the tabernacle of the testimony.
Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
54 And the children of Israel did so: all, just as the Lord had commanded Moses, so did they.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Numbers 1 >