< Numbers 4 >
1 And the Lord spoke unto Moses and unto Aaron, saying,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 Take the sum of the sons of Kehath from among the sons of Levi, after their families, by their divisions,
“Ka iye àwọn ọmọ Kohati láàrín àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
3 From thirty years old and upward even until fifty years old, all that are fitted for the service, to do work at the tabernacle of the congregation.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
4 This shall be the service of the sons of Kehath at the tabernacle of the congregation: The most holy things.
“Wọ̀nyí ni iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Kohati nínú àgọ́ àjọ, láti tọ́jú àwọn ohun èlò mímọ́ jùlọ.
5 And Aaron shall come with his sons, when the camp setteth forward, and they shall take down the vail of the separation, and cover therewith the ark of the testimony;
Nígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sí aṣọ ìbòrí rẹ̀, wọn yóò sì fi bo àpótí ẹ̀rí.
6 And they shall put over it a covering of badgers' skins, and they shall spread over all a cloth wholly of blue [woollen yarn], and they shall put in its staves.
Wọn yóò sì fi awọ ewúrẹ́ bò ó, lórí awọ ewúrẹ́ yìí ni wọn ó tẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
7 And over the table of the showbread shall they spread a cloth of blue, and put thereon the dishes, and the spoons, and the tubes, and the staves of the covering; and the continual bread shall be thereon:
“Lórí tábìlì àkàrà ìfihàn ni kí wọn ó na aṣọ aláró kan sí, kí wọn kí ó sì fi àwopọ̀kọ́ sórí rẹ̀, àti ṣíbí àti àwokòtò àti ìgò fún ọrẹ ohun mímu; àti àkàrà ìgbà gbogbo ní kí ó wà lórí rẹ̀.
8 And they shall spread over them a cloth of scarlet, and cover the same with a covering of badgers' skins; and they shall put in its staves.
Lórí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọn yóò da, wọn ó tún fi awọ ewúrẹ́ bò ó, wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
9 And they shall take a cloth of blue, and cover the candlestick of the lighting, and its lamps, and its tongs, and its snuff-dishes, and all the oil-vessels thereof, wherewith they minister by it:
“Kí wọn kí ó sì mú aṣọ aláwọ̀ aláró kan, kí wọn kí ó sì fi bo ọ̀pá fìtílà àti fìtílà rẹ̀, àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alumagaji rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò òróró rẹ̀, èyí tí wọ́n fi ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
10 And they shall put it and all its vessels within a covering of badgers' skins, and they shall put it upon a barrow.
Kí wọn ó fi awọ ẹran yí fìtílà àti gbogbo ohun èlò rẹ, kí wọn kí ó sì gbé e lé orí férémù tí wọn yóò fi gbé e.
11 And over the golden altar shall they spread a cloth of blue, and cover it with a covering of badgers' skins; and they shall put in its staves.
“Ní orí pẹpẹ wúrà ni kí wọn ó tẹ́ aṣọ aláró kan sí, wọn yóò sì fi awọ seali bò ó, kí wọ́n sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
12 And they shall take all the vessels of the service, wherewith they minister in the sanctuary, and put them in a cloth of blue, and cover them with a covering of badgers' skins; and they shall put them on a barrow.
“Kí wọn kó gbogbo ohun èlò tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ ìsìn ní ibi mímọ́, kí wọn ó fi aṣọ aláwọ̀ búlúù yìí, kí wọn ó sì fi awọ seali bò ó, kí wọn ó sì fi gbé wọn ka orí férémù.
13 And they shall take away the ashes from the altar, and spread over it a cloth of purple;
“Kí wọn ó kó eérú kúrò lórí pẹpẹ idẹ, kí wọn ó sì tẹ́ aṣọ aláwọ̀ àlùkò lé e lórí.
14 And they shall put upon it all its vessels, wherewith they minister upon it, the fire-pans, the forks, and the shovels, and the basins, all the vessels of the altar; and they shall spread over it a covering of badgers' skins, and put in its staves.
Nígbà náà ni kí wọn ó kó gbogbo ohun èlò fún iṣẹ́ ìsìn níbi pẹpẹ, títí dórí àwo iná, fọ́ọ̀kì ẹran, ọkọ́ eérú àti àwokòtò. Kí wọn ó fi awọ ewúrẹ́ bo gbogbo rẹ̀, kí wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
15 And when Aaron and his sons have thus made an end of covering the sanctuary, and all the vessels of the sanctuary, when the camp is to set forward: then shall, after that, the sons of Kehath come to carry it; but they shall not touch any holy thing, lest they die; these are the things which the sons of Kehath are to carry at the tabernacle of the congregation.
“Lẹ́yìn tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti parí bíbo ibi mímọ́ àti gbogbo ohun èlò ibi mímọ́, nígbà tí àgọ́ bá sì ṣetán láti tẹ̀síwájú, kí àwọn ọmọ Kohati bọ́ síwájú láti gbé e, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ohun mímọ́ kankan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀ wọn ó kú. Àwọn ọmọ Kohati ni yóò gbé gbogbo ohun tó wà nínú àgọ́ ìpàdé.
16 And under the supervision of Elazar the son of Aaron the priest shall be the oil for the lighting, and the incense of spices, and the daily meat-offering, and the anointing-oil; the supervision of all the tabernacle, and of all that is therein, over the sanctuary, and over its vessels.
“Iṣẹ́ Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni ṣíṣe àbojútó òróró fìtílà, tùràrí dídùn, ẹbọ ohun jíjẹ ìgbà gbogbo àti òróró ìtasórí. Kí ó jẹ́ alábojútó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ àgọ́ àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò ibi mímọ́.”
17 And the Lord spoke unto Moses and unto Aaron, saying,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
18 Do ye not cause the tribe of the families of the Kehathites to be cut off from among the Levites;
“Rí i pé a kò gé ẹ̀yà Kohati kúrò lára àwọn ọmọ Lefi.
19 But thus do unto them, that they may live, and not die, when they approach unto the most holy things: Aaron and his sons shall go in, and appoint them, every one, to his service and to his burden;
Nítorí kí wọ́n lè yè, kí wọ́n má ba à kú nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ tòsí àwọn ohun mímọ́ jùlọ: Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó wọ ibi mímọ́ láti pín iṣẹ́ oníkálùkù àti àwọn ohun tí wọn yóò gbé.
20 That they may not go in to see when the holy things are covered, and die.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Kohati kò gbọdọ̀ wọlé láti wo àwọn ohun mímọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ ìṣẹ́jú kan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kú.”
21 And the Lord spoke unto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
22 Take also the sum of the sons of Gershon, by their divisions, after their families;
“Tún ka iye àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
23 From thirty years old and upward until fifty years old shalt thou number them; all that are fitted for the service, to do work in the tabernacle of the congregation.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
24 This shall be the service of the families of the Gershunites, to serve, and to carry:
“Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni, bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ àti ní ẹrù rírù.
25 They shall carry the curtains of the tabernacle, and of the tent of the congregation, its covering, and the covering of the badgers' skins that is over it above, and the hanging for the door of the tabernacle of the congregation,
Àwọn ni yóò máa ru àwọn aṣọ títa ti àgọ́, ti àgọ́ ìpàdé àti ìbòrí rẹ̀, àti awọ ewúrẹ́ tí a fi bò ó, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
26 And the hangings of the court, and the hanging for the door of the gate of the court, which is by the tabernacle and by the altar round about, and their cords, and all the vessels of their service; and all that is delivered to them shall they perform.
aṣọ títa ti àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí àgbàlá, okùn àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ ìsìn, àti ohun gbogbo tí à ń lò fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ó máa sìn. Àwọn ọmọ Gerṣoni ni yóò ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ pẹ̀lú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
27 By the order of Aaron and his sons shall be all the service of the sons of the Gershunites, in all their carrying, and in all their service: and ye shall designate unto them in charge all which they have to carry.
Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gerṣoni yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.
28 This is the service of the families of the sons of the Gershunites at the tabernacle of the congregation; their charge shall be under the supervision of Ithamar the son of Aaron the priest.
Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gerṣoni ni àgọ́ ìpàdé Itamari, ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.
29 The sons of Merari, shalt thou number after their families, by their divisions;
“Ka iye àwọn ọmọ Merari nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
30 From thirty years old and upward, even until fifty years old, shalt thou number them, every one that is fitted for the service, to do the work of the tabernacle of the congregation.
Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
31 And this is what is confided to them to carry, regarding all their service at the tabernacle of the congregation: The boards of the tabernacle, and its bars, and its pillars, and its sockets,
Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú àgọ́ ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábùú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,
32 And the pillars of the court round about, and their sockets, and their pins, and their cords, with all their instruments, and all which belongeth thereto; and by name shall ye designate [to them] the vessels which are confided to them to carry.
pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn, kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un.
33 This is the service of the families of the sons of Merari, regarding all their service, at the tabernacle of the congregation, under the supervision of Ithamar the son of Aaron, the priest.
Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Merari, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.”
34 And Moses with Aaron and the princes of the congregation numbered the sons of the Kehathites after their families, and after their divisions,
Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kohati nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
35 From thirty years old and upward, even until fifty years old, every one that was fitted for the service, for the work at the tabernacle of the congregation.
Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ ìpàdé.
36 And those that were numbered of them after their families were two thousand seven hundred and fifty.
Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín làádọ́ta.
37 These were they that were numbered of the families of the Kehathites, all that could do service at the tabernacle of the congregation, whom Moses with Aaron numbered by the order of the Lord through the hand of Moses.
Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé; tí Mose àti Aaroni kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
38 And those that were numbered of the sons of Gershon, after their families, and after their divisions,
Wọ́n ka àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
39 From thirty years old and upward, even until fifty years old, every one that was fitted for the service, for the work at the tabernacle of the congregation,
Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, gbogbo àwọn tó lè ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
40 Even those that were numbered of them, after their families, after their divisions, were two thousand and six hundred and thirty.
Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá ó lé ọgbọ̀n.
41 These are they that were numbered of the families of the sons of Gershon, all that could do service at the tabernacle of the congregation, whom Moses with Aaron numbered by the order of the Lord.
Èyí jẹ́ àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Gerṣoni, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé. Mose àti Aaroni ṣe bí àṣẹ Olúwa.
42 And those that were numbered of the families of the sons of Merari, after their families, after their divisions,
Wọ́n ka àwọn ọmọ Merari nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
43 From thirty years old and upward, even until fifty years old, every one that was fitted for the service, for the work at the tabernacle of the congregation.
Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
44 Even those that were numbered of them after their families, were three thousand and two hundred.
Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún.
45 These are those that were numbered of the families of the sons of Merari, whom Moses with Aaron numbered by the order of the Lord through the hand of Moses.
Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Merari. Mose àti Aaroni kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
46 All those that were numbered of the Levites, whom Moses with Aaron and the chiefs of Israel numbered, after their families, and after their divisions,
Gbogbo àwọn tí a kà nínú àwọn ọmọ Lefi, ti Mose àti Aaroni àti àwọn olórí Israẹli kà, nípa ìdílé wọn àti gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
47 From thirty years old and upward, even until fifty years old, every one that came to do the service of the ministry, and the service of the carrying at the tabernacle of the congregation,
Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn tó sì ń ru àwọn ẹrù inú Àgọ́ ìpàdé.
48 Even those that were numbered of them, were eight thousand and five hundred and eighty.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá lé lẹ́gbàarin ó dín ogún.
49 By the order of the Lord through the hand of Moses, did he appoint them, every one to his proper service, and to his proper carrying: and they were numbered, as the Lord had commanded Moses.
Wọ́n yan iṣẹ́ àti àwọn ohun tí ẹni kọ̀ọ̀kan yóò máa gbé fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.