< Numbers 27 >

1 And there came nigh the daughters of Zelophehad, the son of Chepher, the son of Gil'ad, the son of Machir, the son of Manasseh, of the families of Menasseh the son of Joseph: and these are the names of his daughters, Machlah, No'ah, and Choglah, and Milcah, and Tirzah.
Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
2 And they stood before Moses, and before Elazar the priest, and before the princes, and all the congregation, by the door of the tabernacle of the congregation, saying,
Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
3 Our father died in the wilderness; but he was not among the company of those that gathered themselves together against the Lord in the company of Korach; but in his own sin he died, and sons he had not.
“Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
4 Why should the name of our father be done away from the midst of his family, because he hath no son? Give unto us a possession among the brothers of our father.
Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
5 And Moses brought their cause before the Lord.
Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
6 And the Lord spoke unto Moses, saying,
Olúwa sì wí fún un pé,
7 The daughters of Zelophehad speak rightly: thou shalt indeed give them a possession as an inheritance among the brothers of their father; and thou shalt cause the inheritance of their father to pass unto them.
“Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
8 And unto the children of Israel shalt thou speak, saying, If a man die, and have no son, then shall ye cause his inheritance to pass unto his daughter.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
9 And if he have no daughter, then shall ye give his inheritance unto his brothers.
Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
10 And if he have no brothers, then shall ye give his inheritance unto his father's brothers.
Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
11 And if his father have no brothers, then shall ye give his inheritance unto his kinsman that is next to him of his family, and he shall inherit it; and it shall be unto the children of Israel a statute of justice, as the Lord hath commanded Moses.
Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
12 And the Lord said unto Moses, Go thou up unto this mount of 'Abarim, and see the land which I have given unto the children of Israel.
Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
13 And when thou hast seen it, then shalt thou also be gathered unto thy people, as Aaron thy brother hath been gathered.
Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
14 Because ye rebelled against my order in the desert of Zin, at the quarreling of the congregation, to sanctify me through the waters before their eyes: these are the waters of Meribah in Kadesh, in the wilderness of Zin.
nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
15 And Moses spoke unto the Lord, saying,
Mose sọ fún Olúwa wí pé,
16 Let the Lord, the God of the spirits of all flesh, appoint a man over the congregation,
“Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
17 Who may go out before them, and who may come in before them, and who may lead them out, and who may bring them in; that the congregation of the Lord be not as a flock which have no shepherd.
láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
18 And the Lord said unto Moses, Take to thyself Joshua the son of Nun, a man in whom there is a spirit, and thou shalt lay thy hand upon him;
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
19 And thou shalt cause him to stand before Elazar the priest, and before all the congregation; and thou shalt give him a charge before their eyes.
Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
20 And thou shalt put some of thy greatness upon him; in order that all the congregation of the children of Israel may be obedient.
Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
21 And before Elazar the priest shall he stand, and he shall ask of him after the judgment of the Urim before the Lord: at his direction shall they go out, and at his direction shall they come in, he, and all the children of Israel with him, and all the congregation.
Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
22 And Moses did, as the Lord had commanded him; and he took Joshua, and caused him to stand before Elazar the priest, and before all the congregation;
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
23 And he laid his hands upon him, and gave him a charge: as the Lord had commanded by the hand of Moses.
Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Numbers 27 >