< Lamentations 5 >

1 Remember, O Lord, what hath occurred to us, look down, and behold our disgrace.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Our inheritance is turned over to strangers, our houses to aliens.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Orphans are we become, and [we are] without a father, our mothers are like widows.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 Our water have we drunk for money: our wood cometh to us for a purchase price.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Up to our necks are we pursued: we are fatigued, and no rest is allowed us.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 To Egypt do we stretch out our hand, to Asshur, to be satisfied with bread.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Our fathers have sinned, and are no more; but we have indeed to bear their iniquities.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Servants rule over us: no one delivereth us out of their hand.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 At the peril of our life must we bring home our bread, because of the sword of the wilderness.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Our skin gloweth like an oven, because of the heat of famine.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Women have they ravished in Zion, virgins, in the cities of Judah.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Princes were hanged up by their hand: the faces of elders were not honored.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Young men they bore to the mill, and boys stumbled under the wood.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 The elders have ceased from the gate, young men, from their singing.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 Ceased hath the joy of our heart: our dance is changed into mourning.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 Fallen is the crown of our head: woe to us, for we have sinned.
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Because of this is our heart made sick; for these things are our eyes dimmed;
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Because of the mount of Zion which is wasted, foxes walk about on it.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 O thou, Lord, wilt truly abide for ever, thy throne existeth throughout all generations.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Wherefore wilt thou forget us for ever! wilt thou forsake us for so long a time?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Cause us to return, O Lord, unto thee, and we will return: renew our days as of old.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 For wouldst thou entirely reject us, be wroth with us to the uttermost?
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentations 5 >