< Joshua 18 >
1 And the whole congregation of the children of Israel assembled together at Shiloh, and set up there the tabernacle of the congregation. And the land was subdued before them.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
2 And there remained among the children of Israel, that had not yet received their inheritance, seven tribes.
ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
3 And Joshua said unto the children of Israel, How long will ye show yourselves slack to go to take possession of the land, which the Lord the God of your fathers hath given to you!
Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
4 Furnish for yourselves three men for each tribe; and I will send them out, and they shall arise, and walk through the land, and describe it according to their inheritance, and come again to me.
Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
5 And they shall divide it into seven parts: Judah shall remain on his boundary at the south, and the house of Joseph shall remain on their boundary at the north.
Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
6 But you shall make a description of the land in seven parts, and bring it hither to me; and I will cast the lot for you here, before the Lord our God.
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
7 For to the Levites there is no portion among you; for the priesthood of the Lord is their inheritance; and Gad, and Reuben, and half the tribe of Menasseh have already received their inheritance beyond the Jordan, at the east, which Moses the servant of the Lord gave to them.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
8 And the men arose, and went away; and Joshua charged those that went to describe the land, saying, Go and walk through the land, and describe it, and return again to me; and here will I cast the lot for you before the Lord, in Shiloh.
Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
9 And the men went and passed through the land, and described it according to the cities in seven parts in a book; and they came again to Joshua to the camp at Shiloh.
Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
10 And Joshua cast the lot for them in Shiloh before the Lord; and Joshua divided there the land unto the children of Israel according to their divisions.
Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
11 And the lot of the tribe of the children of Benjamin came up according to their families; and the boundary of their lot came forth between the children of Judah and the children of Joseph.
Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
12 And their boundary was on the north side [starting] from the Jordan; and the boundary went up to the side of Jericho on the north, and went up through the mountains westward; and its terminations were at the wilderness of Beth-aven.
Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
13 And the boundary went over from there toward Luz, to the south side of Luz, which is Beth-el; and the boundary descended to 'Atroth-addar, upon the mount that is on the south side of the lower Beth-choron.
Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
14 And the border extended [thence], and fetched a compass to the west side, to the south of the mount that is before Beth-choron at the south; and its terminations were at Kiryath-ba'al, which is Kiryath-ye'arim, a city of the children of Judah: this was the west side.
Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
15 And the south side commenced from the end of Kiryath-ye'arim, and the boundary went out on the west, and went out to the spring of the waters of Nephtoach:
Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
16 And the boundary went down to the end of the mountain that is before the valley of the son of Hinnom, and which is in the valley of Rephaim at the north, and descended to the valley of Hinnom, to the side of the Jebusi on the south, and descended to 'Enrogel,
Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
17 And extended northwardly, and went forth to 'En-shemesh, and went forth toward Geliloth, which is opposite to the ascent of Adummim, and descended to Eben-bohan the son of Reuben,
Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
18 And passed along on this side opposite to 'Arabah northward; and went down unto 'Arabah;
Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
19 And the boundary passed along to the side of Beth-choglah northward; and the terminations of the border were at the north bay of the Salt Sea at the south end of the Jordan: this was the south boundary.
Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
20 And the Jordan bounded it on the east side. This was the inheritance of the children of Benjamin, by its boundaries round about, according to their families.
Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
21 Now these were the cities of the tribe of the children of Benjamin according to their families, Jericho, and Beth-choglah, and 'Emekkeziz,
Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
22 And Beth-ha'arabah, and Zemarayim, and Beth-el,
Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
23 And Avvim, and Parah, and 'Ophrah,
Affimu, Para, Ofira
24 And Kephar-ha'ammonah, and 'Ophni, and Geba': twelve cities with their villages.
Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
25 Gib'on, and Ramah, and Beeroth,
Gibeoni, Rama, Beeroti,
26 And Mizpeh, and Kephirah, and Mozah,
Mispa, Kefira, Mosa,
27 And Rekem, and Yirpeel, and Taralah,
Rekemu, Irpeeli, Tarala,
28 And Zela', Eleph, and Jebusi, which is Jerusalem, Gib'ath, and Kiryath: fourteen cities with their villages. This is the inheritance of the children of Benjamin according to their families.
Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.