< Job 19 >

1 Then answered Job, and said,
Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:
2 How long will ye grieve my soul, and crush me with words?
“Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí, tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?
3 These ten times have ye reproached me: ye are not ashamed when ye show yourselves as strangers to me.
Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí; ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.
4 Yea, if it be indeed that I have erred, let my error remain with myself.
Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́, ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.
5 But if indeed ye wish to magnify yourselves above me, and to prove against me my disgrace:
Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́, tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,
6 Then know for certain that God hath bent me down, and hath laid his net all around me.
kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú, ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.
7 Behold, I cry out concerning the violence [done me], but I am not answered: I entreat aloud, but there is no justice.
“Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi; mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.
8 My road hath he fenced up, so that I cannot pass out; and on my paths he placeth darkness.
Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá, Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.
9 My glory hath he stripped from me, and removed the crown of my head.
Ó ti bọ́ ògo mi, ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.
10 He hath pulled me down on every side, and I am going hence; and he hath rooted up like a tree my hope.
Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo, ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.
11 He hath also kindled against me his wrath, and he counteth me with himself as one of his adversaries.
Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi, ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.
12 Altogether come on his troops, and make level against me their way, and encamp round about my tent.
Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi, wọ́n sì mọ odi yí mi ká, wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.
13 My brothers hath he removed far from me, and my acquaintance are entirely estranged from me.
“Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré, àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.
14 My near of kin have withdrawn, and those befriended by me have forgotten me.
Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn, àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.
15 Ye that sojourn in my house, and my maid-servants, regard me as a stranger: an alien am I become in their eyes.
Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì; èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.
16 I call for my servant, but he will not answer, though I were to entreat him with my mouth.
Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn; mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.
17 My breath is become nauseous to my wife, and my caressing, to the children of my own body.
Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.
18 Yea, children even despise me: I rise up, but they speak against me.
Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín, mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.
19 All that have had my confidence abominate me; and those whom I have loved are turned against me.
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi, àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.
20 To my skin and to my flesh my bones do cleave, and I must sustain myself with the gums of my teeth.
Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi, mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.
21 Spare me, spare me, O ye, my friends; for the hand of God hath touched me.
“Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi, ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.
22 Why will ye persecute me as God [hath done], and will never be satisfied with my flesh?
Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?
23 Oh who would but grant, that my words might be written down! oh who would grant that they were entered in a book!
“Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!
24 That they were hewn with an iron pen and [blackened with] lead for eternity in the hard rock!
Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ wọ́n sínú àpáta fún láéláé.
25 And well I know that my redeemer liveth, and that he will remain as the last after the creatures of the dust [are passed away];
Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;
26 And after my skin is cut to pieces will this be: and then freed from my body shall I behold God;
àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,
27 Whom I shall myself behold to my happiness, and whom my eyes will see, and not as a stranger, [when even] my reins are consumed within my bosom.
ẹni tí èmi ó rí fún ara mi, tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn; ọkàn mi sì dákú ní inú mi.
28 But if ye should say, How will we pursue him? seeing the root of the matter is found in me:
“Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa ó ti lépa rẹ̀ tó! Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’
29 Then have dread for yourselves of the sword; for the wrath [which ye excite] is an iniquity that bringeth the sword; in order that ye may know there is one that judgeth [in the world].
kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù, nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà, kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”

< Job 19 >