< Jeremiah 52 >
1 One and twenty years was Zedekiah old when he became king, and eleven years did he reign in Jerusalem. And his mother's name was Chamutal the daughter of Jeremiah of Libnah.
Sedekiah jẹ́ ọmọ ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Ọdún mọ́kànlá ló fi jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hamutali ọmọ Jeremiah; láti Libina ló ti wá.
2 And he did what is evil in the eyes of the Lord, in accordance with all that Jehoyakim had done.
Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa gẹ́gẹ́ bí Jehoiakimu ti ṣe.
3 For through the anger of the Lord it came to pass against Jerusalem and Judah, till he had cast them out of his presence, that Zedekiah rebelled against the king of Babylon.
Nítorí ìbínú Olúwa ni gbogbo èyí ṣe ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu àti Juda àti ní ìkẹyìn. Ó sì gbà wọ́n gbọ́ ní iwájú rẹ̀. Sedekiah ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Babeli.
4 And it came to pass in the ninth year of his reign, in the tenth month, on the tenth day of the month, that Nebuchadrezzar the king of Babylon came, he and all his army, against Jerusalem, and they encamped against it, and built against it works of attack round about.
Nígbà tí ó di ọdún kẹsànán ti Sedekiah tí ń ṣe ìjọba ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù kẹwàá Nebukadnessari ọba Babeli sì lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọ́n pàgọ́ sí ẹ̀yìn odi ìlú náà; wọ́n sì mọ odi yíká rẹ̀.
5 So the city was placed in a state of siege until the eleventh year of king Zedekiah.
Ìlú náà sì wá lábẹ́ ìhámọ́ títí di ọdún kọkànlá ọba Sedekiah.
6 And in the fourth month, on the ninth day of the month, when the famine was severe in the city, so that there was no bread for the people of the land:
Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù mẹ́rin ìyàn ìlú náà sì ti burú dé ibi pé kò sí oúnjẹ kankan mọ́ fún àwọn ènìyàn láti jẹ.
7 The city was broken in, and all the men of war fled, and went forth out of the city by night by the way of the gate between the two walls, which was near the king's garden; [while the Chaldeans were round about the city; ] and they went by the way of the plain.
Bákan náà, odi ìlú náà ti ya àwọn ọmọ-ogun sì tí sálọ. Wọn fi ìlú náà sílẹ̀ ní òru nípa ojú ọ̀nà tó wà láàrín odi méjèèjì lẹ́bàá ọgbà ọba. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn ará Babeli yìí yí ìlú náà ká. Wọ́n sá gba aginjù lọ.
8 But the army of the Chaldeans pursued after the king, and they overtook Zedekiah in the plains of Jericho: and all his army was scattered from him.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ogun Babeli lépa ọba Sedekiah wọ́n sì le bá ni pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko. Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì pínyà, kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ wọ́n sì túká.
9 And they caught the king, and they brought him up unto the king of Babylon to Riblah in the land of Chamath: and he called him to account.
Wọ́n sì mu ní ìgbèkùn. Wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli, ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati níbẹ̀ ni ó ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀.
10 And the king of Babylon slaughtered the sons of Zedekiah before his eyes: and also all the princes of Judah did he slaughter in Riblah.
Ní Ribla ni ọba Babeli ti pa ọmọkùnrin Sedekiah lójú rẹ̀; ó sì tún pa gbogbo àwọn aláṣẹ Juda.
11 And the eyes of Zedekiah did he blind; and the king of Babylon bound him with brazen fetters, and carried him to Babylon, and put him in the ward-house till the day of his death.
Lẹ́yìn náà, ọba Babeli yọ Sedekiah ní ojú, o sì fi ẹ̀wọ̀n dè é, ó sì gbe e lọ sí Babeli níbi tí ó ti fi sínú ọgbà ẹ̀wọ̀n títí di ọjọ́ ikú rẹ̀.
12 And in the fifth month, on the tenth day of the month, which was the nineteenth year of king Nebuchadrezzar the king of Babylon, came Nebuzaradan, the captain of the guard, [who] served the king of Babylon, unto Jerusalem.
Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù karùn-ún, tí ó jẹ́ ọdún kọkàndínlógún Nebukadnessari ọba Babeli, ni Nebusaradani balógun ìṣọ́ wá sí Jerusalẹmu.
13 And he burnt the house of the Lord, and the king's house: and all the houses of Jerusalem, and all the houses of the great men, did he burn with fire:
Ó dáná sun pẹpẹ Olúwa, ààfin ọba àti gbogbo àwọn ilé Jerusalẹmu. Ó sì dáná sun gbogbo àwọn ilé ńlá ńlá.
14 And all the walls of Jerusalem round about did all the army of the Chaldeans, that were with the captain of the guard, pull down.
Gbogbo àwọn ogun Babeli, tí ó wà lọ́dọ̀ olórí ẹ̀ṣọ́, wó ògiri tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀.
15 And certain of the poorest of the people, and the residue of the people that had been left in the city, and the deserters, that had run away to the king of Babylon, and the rest of the multitude, did Nebuzaradan the captain of the guard carry away into exile.
Nebusaradani balógun ìṣọ́ kó gbogbo àwọn tálákà àti gbogbo àwọn tí ó kù ní ìlú, ní ìgbèkùn lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn tí ó ya lọ, tí ó sì ya tọ ọba Babeli lọ, àti ìyókù àwọn ènìyàn náà.
16 But certain of the poorest of the land did Nebuzaradan the captain of the guard leave for vine-dressers and for husbandmen.
Ṣùgbọ́n Nebusaradani, balógun ìṣọ́ fi àwọn tálákà tó kú ní ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà àti ro oko.
17 Also the pillars of copper that were in the house of the Lord, and the bases, and the copper sea that was in the house of the Lord, did the Chaldeans break, and they carried off all their copper to Babylon.
Àwọn ará Babeli fọ́ ọ̀wọ̀n idẹ wọ̀n-ọn-nì àti àwọn ìjókòó wọ̀n-ọn-nì, àti agbada idẹ títóbi wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ilé Olúwa, àwọn ará Babeli fọ́ túútúú, wọ́n sì kó gbogbo idẹ náà lọ sí Babeli.
18 And the pots, and the shovels, and the knives, and the bowls, and the spoons, and all the vessels of copper wherewith they used to perform the service, did they take away.
Bákan náà, wọ́n tún kó àwọn ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọkọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, ṣíbí wọ̀n-ọn-nì àti gbogbo ohun èlò idẹ tí wọ́n ń lò níbi pẹpẹ lọ.
19 And the basins, and the censers, and the bowls, and the pots, and the candlesticks, and the spoons, and the purifying-tubes: of what was of gold the gold, and of what was of silver the silver, did the captain of the guard take away.
Balógun ìṣọ́ náà kó àwokòtò wọ̀n-ọn-nì, ohun ìfọnná wọ̀n-ọn-nì, ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, ṣíbí wọ̀n-ọn-nì àti ago wáìnì wọ̀n-ọn-nì; èyí tí a fi wúrà àti fàdákà ṣe lọ.
20 The two pillars, the one sea, and the twelve copper oxen that served instead of the bases, which king Solomon had made for the house of the Lord: the copper of all these vessels could not be weighed.
Àwọn ọ̀wọ́n méjì, agbada ńlá kan àti àwọn màlúù idẹ méjìlá tí ó wà lábẹ́ ìjókòó alágbéká tí Solomoni ọba ṣe fún ilé Olúwa, idẹ ni gbogbo ohun èlò wọ̀nyí, ó ju èyí tí a lè wọ́n lọ.
21 And as regardeth the pillars, eighteen cubits was the height of each one pillar; and a thread of twelve cubits would compass it; and its thickness was four fingers: it was hollow.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọ̀wọ́n yìí ni ga ní ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ méjìdínlógún; okùn ìgbọ̀nwọ́ méjìlá sì yí i ká. Ọ̀kọ̀ọ̀kan nípọn tó ìka mẹ́rin, wọ́n sì ní ihò nínú.
22 And a capital was upon it of copper; and the height of the one capital was five cubits, with network and pomegranates upon the capital round about, all of copper. And the like was the case with the second pillar and the pomegranates.
Ọ̀nà orí idẹ kan tó ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gíga, wọ́n sì fi èso pomegiranate ṣe ọ̀ṣọ́ sí i lára yíká. Ọ̀wọ́n kejì sì wà pẹ̀lú èso pomegiranate tí ó jọra.
23 And the pomegranates were ninety and six on every side: all the pomegranates upon the network were one hundred round about.
Pomegiranate mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún ni ó wà ní àwọn ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àpapọ̀ gbogbo pomegiranate sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún kan.
24 And the captain of the guard took Serayah the chief priest, and Zephanyah the priest second in rank, and the three door-keepers;
Balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ mu Seraiah olórí àwọn àlùfáà àti Sefaniah àlùfáà kejì àti àwọn olùṣọ́ ìloro mẹ́ta.
25 And out of the city he took a certain court-officer, who had the supervision of the men of war: and seven men of those that had free access to the kings presence, who were found in the city; and the scribe of the chief of the army, who ordered to the army the people of the land; and sixty men of the people of the land, that were found in the midst of the city;
Nínú àwọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, ó mú ìwẹ̀fà kan, tí ó wà ní ìtọ́jú àwọn ológun, àti àwọn olùdámọ̀ràn ọba méje. Bákan náà, ó tún mu akọ̀wé olórí ogun tí ó wà ní ìtọ́jú títo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti ọgọ́ta nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú náà.
26 And Nebuzaradan the captain of the guard took them, and led them away unto the king of Babylon to Riblah.
Nebusaradani, balógun ìṣọ́ kó gbogbo wọn, ó sì mú wọn tọ ọba Babeli wá ní Ribla.
27 And the king of Babylon smote them, and put them to death in Riblah in the land of Chamath. Thus Judah was carried away into exile out of his own country.
Ọba Babeli sì kọlù wọ́n, ó sì pa wọ́n ní Ribla ni ilẹ̀ Hamati. Báyìí ni a mú Juda kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.
28 This is the people whom Nebuchadrezzar carried away into exile: in the seventh year, three thousand and twenty and three Jews;
Èyí ni iye àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì. Ní ọdún keje ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé mẹ́tàlélógún ará Juda.
29 In the eighteenth year of Nebuchadrezzar from Jerusalem, eight hundred thirty and two persons;
Ní ọdún kejìdínlógún Nebukadnessari o kó ẹgbẹ̀rin ó lé méjìlélọ́gbọ̀n láti Jerusalẹmu.
30 In the three and twentieth year of Nebuchadrezzar, did Nebuzaradan the captain of the guard carry away into exile of the Jews seven hundred forty and five persons; all the persons were four thousand and six hundred.
Ní ọdún kẹtàlélógún àwọn Júù tí Nebusaradani kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín márùn-ún. Gbogbo ènìyàn tí ó kó lápapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀tàlélógún.
31 And it came to pass in the seven and thirtieth year of the exile of Jehoyachin the king of Judah, in the twelfth month, on the five and twentieth day of the month that Evil-merodach the king of Babylon in the [first] year of his reign lifted up the head of Jehoyachin the king of Judah, and brought him forth out of the prison-house;
Ní ọdún kẹtàdínlógójì ti Jehoiakini ọba Juda ni Efili-Merodaki di ọba Babeli. Ó gbé orí Jehoiakini ọba Juda sókè, ó sì tú sílẹ̀ nínú túbú ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù kejìlá.
32 And he spoke kindly with him, and set his throne above the throne of the kings that were with him in Babylon,
Ó ń sọ̀rọ̀ rere fún un, ó sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ga ju ìtẹ́ àwọn ọba tókù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Babeli.
33 And he changed his prison-garments: and he ate bread before him continually all the days of his life.
Nítorí náà, Jehoiakini pàrọ̀ aṣọ túbú rẹ̀, ó sì ń jẹun ní gbogbo ìgbà ní iwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
34 And his allowance was a continual allowance given him by the king, the necessary ration for the day on its day, until the day of his death, all the days of his life.
Ní ojoojúmọ́ ni ọba Babeli ń fún Jehoiakini ní ìpín tirẹ̀ bí ó tí ń bẹ láààyè, títí di ọjọ́ kú rẹ̀.