< Jeremiah 39 >
1 In the ninth year of Zedekiah the king of Judah, in the tenth month, that Nebuchadrezzar the king of Babylon came with all his army against Jerusalem, and they besieged it.
Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
2 [And] in the eleventh year of Zedekiah, in the fourth month, on the ninth day of the month, was the city broken in.
Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
3 And then came all the princes of the king of Babylon, and sat down in the middle gate; [namely, ] Neregal-sharezer, Samgar-nebu, Sarsechim, the chief of the eunuchs, Neregal-sharezer, the chief of the magi, with all the residue of the princes of the king of Babylon.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
4 And it came to pass when Zedekiah the king of Judah saw them, and all the men of war, that they fled, and went forth out of the city by night, by the way of the king's garden, by the gate between the two walls: and he went out by the way of the plain.
Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
5 But the army of the Chaldeans pursued after them, and they overtook Zedekiah in the plains of Jericho; and they took him, and brought him up to Nebuchadnezzar the king of Babylon to Riblah in the land of Chamath: and he called him to account.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
6 And the king of Babylon slaughtered the sons of Zedekiah in Riblah before his eyes; also all the nobles of Judah did the king of Babylon slaughter.
Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
7 And the eyes of Zedekiah did he blind; and he bound him with brazen fetters, to carry him to Babylon.
Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
8 And the house of the king, and the houses of the people did the Chaldeans burn with fire, and the walls of Jerusalem did they pull down.
Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
9 And the rest of the people that remained in the city, and those who had run away that had run away to him, with the rest of the people that remained, did Nebuzaradan the captain of the guard carry off into exile to Babylon.
Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
10 But of the poorest of the people, who had nothing, did Nebuzaradan the captain of the guard leave some in the land of Judah, and gave them vineyards and arable fields at the same time.
Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
11 And Nebuchadrezzar the king of Babylon gave charge concerning Jeremiah through means of Nebuzaradan the captain of the guard, saying,
Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
12 Take him, and direct thy eyes to him, and do him not the least harm; but as he may speak unto thee, even so do thou with him.
“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
13 Then sent Nebuzaradan the captain of the guard, and Nebushazban, the chief of the eunuchs, and Neregal-sharezer, the chief of the magi, and all the chiefs of the king of Babylon, —
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
14 Even they sent, and took Jeremiah out of the court of the prison, and they committed him unto Gedalyahu the son of Achikam the son of Shaphan, to carry him home: and he remained in the midst of the people.
ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 But unto Jeremiah was come the word of the Lord while he was shut up in the court of the prison, saying,
Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
16 Go and say to 'Ebed-melech the Cushi as followeth, Thus hath said the Lord of hosts, the God of Israel, Behold, I will bring my words [to fulfillment] against this city for evil, and not for good; and they shall be accomplished before thee on that day.
“Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
17 But I will deliver thee on that day, saith the Lord; and thou shalt not be given up into the hand of the men of whom thou hast dread.
Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
18 For I will surely let thee escape, and thou shalt not fall by the sword; but thy life shall be unto thee as a booty; because thou hast put thy trust in me, saith the Lord.
Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”