< Jeremiah 1 >
1 The words of Jeremiah the son of Chilkiyahu, one of the priests that were in 'Anathoth in the land of Benjamin;
Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
2 To whom the word of the Lord came in the days of Josiah the son of Amon the king of Judah, in the thirteenth year of his reign,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
3 And who continued [prophet] in the days of Jehoyakim the son of Josiah the king of Judah, until the end of the eleventh year of Zedekiah the son of Josiah the king of Judah, until the carrying away into exile of Jerusalem in the fifth month.
àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
4 And the word of the Lord came unto me, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
5 Before yet I had formed thee in thy mother's body I knew thee; and before thou wast yet come forth out of the womb I sanctified thee: a prophet unto the nations did I ordain thee.
“Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
6 And I said, Ah, Lord Eternal! behold, I know not how to speak; for I am [but] a lad.
Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
7 And the Lord said unto me, Say not, I am [but] a lad; but to whomsoever I may send thee shalt thou go, and whatsoever I may command thee shalt thou speak.
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
8 Be not afraid because of them; for I am with thee to deliver thee, saith the Lord.
Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
9 And the Lord stretched forth his hand, and touched [me] therewith on my mouth; and the Lord said unto me, Behold, I have put my words in thy mouth.
Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
10 See, I have appointed thee this day over the nations and over the kingdoms, to root out, and to pull down, and to destroy, and to throw down: to build up, and to plant.
Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
11 And the word of the Lord came unto me, saying, What seest thou, Jeremiah? And I said, A staff of all almond-tree do I see.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
12 And the Lord said unto me, Thou hast well seen; for I am watching over my word to perform it.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
13 And the word of the Lord came unto me the second time, saying, What seest thou? And I said, A seething pot do I see; and the front thereof is turned from the north.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
14 And the Lord said unto me, Out of the north shall the evil break forth over all the inhabitants of the land,
Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
15 For, lo, I will call unto all the families of the kingdoms of the north, saith the Lord; and they shall come, and they shall set every one his throne at the entrance of the gates of Jerusalem, and upon all its walls round about, and upon [those of] all the cities of Judah.
Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
16 And I will call them to account touching all their wickedness, in that they have forsaken me, and have burnt incense unto other gods, and have bowed down unto the works of their own hands.
Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
17 But do thou gird up thy loins, and arise, and speak unto them all that I may command thee; be not discouraged because of them, lest I humble thee before them.
“Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
18 But I, behold, I have made of thee this day a fortified city, and an iron pillar, and brazen walls over the whole land, against the kings of Judah, against its princes, against its priests, and against the people of the land.
Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
19 And [although] they fight against thee, they shall not prevail against thee; for with thee am I saith the Lord, to deliver thee.
Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.