< Isaiah 35 >

1 The wilderness and the dry land shall be glad thereat; and the desert shall rejoice, and blossom as the lily.
Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn; aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná. Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
2 It shall blossom abundantly, and rejoice, yea, with joy and singing; the glory of the Lebanon shall be given unto it, the elegance of Carmel and Sharon; they indeed shall see the glory of the Lord, and the excellency of our God.
ní títanná yóò tanná; yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin. Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un, ẹwà Karmeli àti Ṣaroni; wọn yóò rí ògo Olúwa, àti ẹwà Ọlọ́run wa.
3 Strengthen ye weak hands, and stumbling knees make ye firm.
Fún ọwọ́ àìlera lókun, mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.
4 Say to the timid of heart, Be strong, fear not: behold, your God, [with] vengeance will he come, with God's recompense; it is he who will come and save you.
Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé, “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù; Ọlọ́run yín yóò wá, òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san; pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́ òun yóò wá láti gbà yín là.”
5 Then shall the eyes of the blind be opened, and the ears of the deaf shall be unstopped.
Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
6 Then shall the lame leap as a hart, and the tongue of the dumb shall sing; for in the wilderness shall waters break out, and brooks in the desert.
Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín, àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀. Odò yóò tú jáde nínú aginjù àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
7 And the sandy waste shall be changed into a pool, and the thirsty land into springs of water: in the habitation of monsters, where each one used to lie, shall be a court for reeds and rushes.
Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà, ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi. Ní ibùgbé àwọn dragoni, níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀, ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.
8 And there shall be a highway and a way, and The holy way, shall it be called; no unclean one shall pass over it; but it shall be [only] theirs; the wayfaring man, and those unacquainted [therewith], shall not go astray.
Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀: a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́. Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà; yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà, àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
9 No lion shall be there, and no ravenous beast shall go up thereon, shall not be found there; but there shall walk the redeemed:
Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀, tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀; a kì yóò rí wọn níbẹ̀. Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
10 And the ransomed of the Lord shall return, and come to Zion with song, with everlasting joy upon their head; gladness and joy shall they obtain, and sorrow and sighing shall flee away.
àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin; ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí. Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn, ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.

< Isaiah 35 >