< Genesis 4 >

1 And the man knew Eve his wife: and she conceived, and bore Cain, and said, I have gotten a man from the Lord.
Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
2 And she bore again, his brother, Abel; and Abel was a keeper of sheep, but Cain was a tiller of the ground.
Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
3 And it came to pass in process of time, that Cain brought of the fruit of the ground and offering unto the Lord.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
4 And Abel—he also brought of the firstlings of his flock, and of the fattest thereof; and the Lord had respect unto Abel and to his offering;
Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
5 But unto Cain and to his offering he had no respect; and it was very displeasing to Cain, and his countenance fell.
ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
6 And the Lord said unto Cain, Why art thou wroth? and why is thy countenance fallen?
Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
7 If thou doest well, shalt thou not be accepted? and if thou doest not well, sin lieth at the door; and unto thee is its desire, but thou canst rule over it.
Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
8 And Cain talked with Abel his brother: and it came to pass when they were in the field, that Cain rose up against Abel his brother, and slew him.
Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
9 And the Lord said unto Cain, Where is Abel they brother? and he said, I know not; am I my brother's keeper?
Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
10 And he said, What hast thou done? the voice of thy brother's blood crieth unto me from the ground.
Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
11 And now be thou cursed from the ground, which hath opened its mouth to receive thy brother's blood from thy hand:
Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
12 When thou tillest the ground, it shall not henceforth yield its strength unto thee; fugitive and vagabond shalt thou be on the earth.
Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
13 And Cain said unto the Lord, My punishment is greater than I can bear.
Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
14 Behold, thou hast driven me out this day from the face of the ground; and from thy face shall I be hid; and if I shall be a fugitive and a vagabond on the earth, it will come to pass, that every one that findeth me will slay me.
Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
15 And the Lord said unto him, Therefore whosoever slayeth Cain, vengeance shall be taken on him seven-fold. And the Lord set a sign unto Cain, that any one finding him should not kill him.
Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
16 And Cain went out from the presence of the Lord, and dwelt in the land of Nod, on the east of Eden.
Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
17 And Cain knew his wife, and she conceived, and bore Enoch; and he built a city, and called the name of the city after the name of his son Enoch.
Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
18 And unto Enoch was born Irad; and Irad begat Mechujael: and Mechujael begat Methushael; and Methushael begat Lemech.
Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
19 And Lemech took unto himself two wives, the name of one was Adah, and the name of the other Zillah.
Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
20 And Adah bore Jabal; he was the father of such as dwell in tents, and have cattle.
Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
21 And his brother's name was Jubal; he was the father of all such as play on the harp and guitar.
Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
22 And Zillah, she also bore Tubal-cain, an artificer in every article of copper and iron; and the sister of Tubal-cain was Naamah.
Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
23 And Lemech said unto his wives, Adah and Zillah, hear my voice; ye wives of Lemech, hearken unto my speech; for I have slain a man to my own wounding, and a young-man to my hurt.
Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
24 If Cain shall be avenged seven-fold, truly Lemech seventy and seven-fold.
Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
25 And Adam knew his wife again, and she bore a son, and called his name Sheth [[Seth]]; for God [said she] hath appointed me another seed instead of Abel, whom Cain slew.
Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
26 And to Sheth, to him also there was born a son; and he called his name Enosh: then began men to call upon the name of the Lord.
Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.

< Genesis 4 >