< Genesis 31 >

1 And he heard the words of Laban's sons, saying, Jacob hath taken away all that was our father's, and of that which was our father's hath he gotten all this wealth.
Jakọbu sì gbọ́ pé àwọn ọmọ Labani ń wí pé, “Jakọbu ti gba gbogbo ohun ìní baba wa, ó sì ti kó ọrọ̀ jọ fún ara rẹ̀ lára àwọn ohun tí í ṣe ti baba wa.”
2 And Jacob beheld the countenance of Laban, and, behold, it was not toward him as before.
Jakọbu sì ṣàkíyèsí pé ìwà Labani sí òun ti yí padà sí ti àtẹ̀yìnwá.
3 And the Lord said unto Jacob, Return unto the land of thy fathers, and to thy birthplace; and I will be with thee.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jakọbu pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”
4 And Jacob sent and called Rachel and Leah to the field unto his flock.
Jakọbu sì ránṣẹ́ pe Rakeli àti Lea sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.
5 And he said unto them, I see your father's countenance, that it is not toward me as before; but the God of my father hath been with me.
Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.
6 And ye know well that with all my power I have served your father.
Ẹ sá à mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,
7 And your father hath deceived me, and changed my wages ten times: but God suffered him not to do me evil.
síbẹ̀síbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.
8 If he said thus, The speckled shall be thy wages: then bore all the flocks speckled: and if he said thus, The ring-streaked shall be thy reward; then bore all the flocks ring-streaked.
Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran onítótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ,’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi onítótòtó.
9 Thus God took away the cattle of your father, and gave them to me.
Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi.
10 And it came to pass at the time that the flocks conceived, that I lifted up my eyes, and saw in a dream, and, behold, the rams which leaped upon the flocks were ring-streaked, speckled, and grizzled.
“Ní àsìkò tí àwọn ẹran ń gùn, mo la àlá mo sì ri pé àwọn òbúkọ tí wọ́n ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì.
11 And an angel of God spoke unto me in the dream, Jacob: and I said, Here am I.
Angẹli Ọlọ́run wí fún mi nínú àlá náà pé, ‘Jakọbu.’ Mo sì wí pé, ‘Èmi nìyí.’
12 And he said, Lift up now thy eyes and see, all the rams which leap upon the flocks are ring-streaked, speckled, and grizzled; for I have seen all that Laban doth unto thee.
Ó sì wí pé, ‘Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wò ó, gbogbo àwọn òbúkọ tí ó ń gun àwọn ẹran jẹ́ onítótòtó, onílà àti alámì, nítorí mo ti rí gbogbo ohun ti Labani ń ṣe sí ọ.
13 I am the God of Beth-el, where thou anointedst a pillar, where thou madest unto me a vow: now arise, get thee out from this land, and return unto the land of thy birth.
Èmi ni Ọlọ́run Beteli, níbi tí ìwọ ti ta òróró sí ọ̀wọ́n, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti sìn mi. Nísinsin yìí, kúrò ní ilẹ̀ yìí kíákíá kí o sì padà sí ilẹ̀ ibi tí a gbé ti bí ọ.’”
14 And Rachel and Leah answered and said unto him, Is there yet any portion or inheritance for us in our father's house?
Nígbà náà ni Rakeli àti Lea dáhùn pé, “Ìpín wo ní a ní nínú ogún baba wa?
15 Were we not counted of him as strangers? for he hath sold us; and he hath quite consumed also our money.
Àjèjì ha kọ́ ni ó kà wá sí? Kì í ṣe torí pé ó tà wá nìkan, ṣùgbọ́n ó ti ná gbogbo owó tí ó gbà lórí wa tán.
16 For all the riches which God hath taken from our father, that is ours, and our children's; now then, whatsoever God hath said unto thee, do.
Dájúdájú gbogbo ọrọ̀ ti Ọlọ́run gbà lọ́wọ́ baba wa fún ọ, tiwa àti ti àwọn ọmọ wa ní í ṣe. Nítorí náà ohun gbogbo tí Ọlọ́run bá pàṣẹ fun ọ láti ṣe ni kí ìwọ kí ó ṣe.”
17 Then Jacob rose up, and set his sons and his wives upon camels;
Nígbà náà ni Jakọbu gbé àwọn ọmọ àti aya rẹ̀ gun ìbákasẹ.
18 And he led away all his cattle, and all his goods which he had gotten, the cattle of his acquiring, which he had gotten in Padan-aram, to go to Isaac his father into the land of Canaan.
Ó sì da gbogbo agbo ẹran rẹ̀ ṣáájú pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ tí ó ti kójọ ni Padani-Aramu, láti lọ sí ọ̀dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni ilẹ̀ Kenaani.
19 And Laban was gone to shear his sheep; and Rachel stole the images that were her father's.
Nígbà tí Labani sì lọ láti rẹ́run àgùntàn, Rakeli sì jí àwọn ère òrìṣà ilé baba rẹ̀.
20 And Jacob stole away unawares to Laban the Syrian, by not letting him know that he was going to flee.
Síwájú sí i, Jakọbu tan Labani ará Aramu, nítorí kò sọ fún un wí pé òun ń sálọ.
21 And he fled with all that he had; and he rose up, and passed over the river, and set his face toward the mount Gilead.
Ó sì sálọ pẹ̀lú ohun gbogbo tí ó ni, ó sì la odò kọjá (Eufurate), ó sì kọrí sí àwọn ilẹ̀ olókè ti Gileadi.
22 And it was told to Laban on the third day that Jacob was fled.
Ní ọjọ́ kẹta ni Labani gbọ́ pé Jakọbu ti sálọ.
23 And he took his brethren with him, and pursued after him a seven days' journey; and he overtook him at the mount of Gilead.
Ó sì mú àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì lépa Jakọbu, ó sì lépa wọn fún ọjọ́ méje, ó sì bá wọn ní òkè Gileadi.
24 And God came to Laban, the Syrian, in a dream of the night, and said unto him, Take thou heed that thou speak not to Jacob either good or bad.
Ọlọ́run sì yọ sí Labani ará Aramu lójú àlá ní òru, ó sì wí fun un pé, “Ṣọ́ra, má ṣe sọ ohunkóhun fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.”
25 Then Laban overtook Jacob; now Jacob had pitched his tent on the mount, and Laban with his brethren pitched on the mount of Gilead.
Jakọbu ti pa àgọ́ rẹ̀ si orí òkè kan, nígbà tí Labani bá a. Labani àti àwọn tí ó wá pẹ̀lú rẹ̀ sì pàgọ́ tì wọ́n sí ilẹ̀ òkè Gileadi.
26 And Laban said to Jacob, What hast thou done, that thou hast stolen away unawares to me, and led away my daughters, as captives taken with the sword.
Nígbà náà ni Labani wí fún Jakọbu pé, “Èwo ni ìwọ ṣe yìí? Tí ìwọ sì tàn mi, ó sì kó àwọn ọmọbìnrin mi bi ìgbèkùn tí a fi idà mú.
27 Wherefore didst thou flee away secretly, and steal away from me; and why didst thou not tell me, that I might have sent thee away with mirth, and with songs, with tabret, and with harp?
Èéṣe tí ìwọ yọ́ lọ tí ìwọ sì tàn mi? Kí ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé ìwọ ń lọ, kí èmi fi ayọ̀ àti orin, pẹ̀lú ìlù àti ohun èlò orin sìn ọ́.
28 And [why] hast thou not suffered me to kiss my sons and my daughters? now thou hast acted foolishly in so doing.
Ìwọ kò tilẹ̀ jẹ́ kí èmi fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ mi lẹ́nu, pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin mi pé ó dìgbà? Ìwọ ṣiwèrè ní ohun tí ìwọ ṣe yìí.
29 It is in the power of my hand to do you hurt; but the God of your father spoke unto me yesternight, saying, Take thou heed that thou speak not to Jacob either good or bad.
Mo ní agbára láti ṣe ọ ni ibi, ṣùgbọ́n ní òru àná, Ọlọ́run baba rẹ sọ fún mi pé, kí èmi ṣọ́ra, kí èmi má ṣe sọ ohun kan fún Jakọbu, ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
30 And now, thou wouldst needs be gone, because thou greatly longedst after thy father's house; [yet] wherefore hast thou stolen my gods.
Nísinsin yìí, ìwọ ti lọ nítorí ìwọ fẹ́ láti padà lọ sí ilé baba rẹ, ṣùgbọ́n èéṣe tí ìwọ fi jí àwọn òrìṣà mi?”
31 And Jacob answered and said to Laban, Because I was afraid, for I said, Peradventure thou wouldst take by force thy daughters from me.
Jakọbu dá Labani lóhùn pé, “Ẹ̀rù ni ó bà mi nítorí, mo rò pé ìwọ le fi tipátipá gba àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ́wọ́ mi.
32 With whomsoever thou findest thy gods, let him not live; before our brethren seek out thou what is thine with me, and take it to thee; but Jacob knew not that Rachel had stolen them.
Ṣùgbọ́n bí o bá ri ẹnikẹ́ni pẹ̀lú ère rẹ, kí ẹni náà di òkú. Ó tún wí pé, níwájú gbogbo ìbátan wa báyìí, wò ó fúnra rẹ̀, bí o bá rí ohunkóhun tí í ṣe tìrẹ, mú un.” Jakọbu kò sì mọ̀ pé, Rakeli ni ó jí àwọn òrìṣà náà.
33 And Laban went into the tent of Jacob, and into the tent of Leah, and into the tent of the two maid-servants; but he found nothing; he then went out of the tent of Leah, and entered into Rachel's tent.
Labani sì lọ sínú àgọ́ Jakọbu àti ti Lea àti ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì, kò sì rí ohunkóhun. Lẹ́yìn ìgbà tí ó jáde nínú àgọ́ Lea ni ó lọ sí àgọ́ Rakeli.
34 Now Rachel had taken the images, and put them in the saddle-cushion of the camel, and sat upon them; and Laban searched all the tent, and found nothing.
Rakeli sì gbé àwọn òrìṣà náà sínú gàárì ìbákasẹ, ó sì jókòó lé e lórí. Labani sì wá gbogbo inú àgọ́, kò sì rí ohunkóhun.
35 And she said to her father, Let it not displease my lord that I cannot rise up before thee; for the custom of women is upon me; and thus he searched, but found not the images.
Rakeli sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Má ṣe bínú pé èmi ò le dìde dúró níwájú rẹ baba à mi, ohun tí ó fà á ni pé, mò ń ṣe nǹkan oṣù lọ́wọ́.” Ó sì wá àgọ́ kiri, kò sì rí àwọn òrìṣà ìdílé náà.
36 Now Jacob became wroth, and quarrelled with Laban; and Jacob answered and said to Laban, What is my trespass? what is my sin, that thou hast so hotly pursued after me?
Inú sì bí Jakọbu, ó sì pe Labani ní ìjà pé, “Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ tí ìwọ fi ń lépa mi bí ọ̀daràn?
37 Although thou hast searched all my goods, what hast thou found of all the articles of thy household? set it here before my brethren and thy brethren, that they may judge between us both.
Nísinsin yìí tí ìwọ ti tú gbogbo ẹrù mi wò, kí ni ohun tí í ṣe tirẹ̀ tí ìwọ rí? Kó wọn kalẹ̀ báyìí níwájú gbogbo ìbátan rẹ àti tèmi, kí wọn kí ó sì ṣe ìdájọ́ láàrín àwa méjèèjì.
38 These twenty years have I been with thee: thy ewes and thy she-goats have not cast their young; and the rams of thy flock have I not eaten.
“Mo ti wà lọ́dọ̀ rẹ fún ogún ọdún, àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ rẹ kò sọnù bẹ́ẹ̀ n kò pa ọ̀kan jẹ rí nínú àwọn àgbò rẹ.
39 That which was torn of beasts I brought not unto thee; I had to bear the loss of it, of my hand didst thou require it, whatever was stolen by day, or stolen by night.
Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fàya, èmi ni ó fi ara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi.
40 [Where] I was in the day the heat consumed me, and the frost by night; and my sleep departed from my eyes.
Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.
41 These twenty years have I been in thy house; I have served thee fourteen years for thy two daughters, and six years for thy flocks: and thou hast changed my wages ten times.
Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.
42 Except the God of my father, the God of Abraham, and the Fear of Isaac, had been with me, surely thou hadst now sent me away empty; my affliction and the labor of my hands God hath seen, and decided yesternight.
Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Abrahamu àti ẹ̀rù Isaaki kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ìbá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ́ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”
43 And Laban answered and said unto Jacob, The daughters are my daughters, and the children are my children, and the flocks are my flocks, and all that thou seest is mine; but as to my daughters, what can I do unto them this day, or unto their children whom they have born?
Labani sì dá Jakọbu lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kí ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?
44 And now, come thou, let us make a covenant, I and thou; and let it be for a witness between me and thee.
Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárín wa.”
45 And Jacob took a stone, and set it up for a pillar.
Jakọbu sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ́n.
46 And Jacob said unto his brethren, Gather stones; and they took stones, and made a heap; and they ate there upon the heap.
Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkìtì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.
47 And Laban called it Yegar-sahadutha; but Jacob called it Galed.
Labani sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jegari-Sahaduta, ṣùgbọ́n Jakọbu pè é ni Galeedi.
48 And Laban said, This heap is a witness between me and thee this day; therefore called he its name Galed;
Labani sì wí pé, “Òkìtì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrín èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Galeedi.
49 And Mitzpah; for he said, The Lord shall watch between me and thee, when we are absent one from the other;
Ó tún pè é ni Mispa nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa ṣọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.
50 If thou shouldst afflict my daughters, or if thou shouldst take other wives besides my daughters, when there is no man with us: see, God is witness between me and thee.
Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrín wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”
51 And Laban said to Jacob, Behold this heap, and behold this pillar, which I have cast up between me and thee;
Labani tún sọ síwájú fún Jakọbu pé, “Òkìtì àti ọ̀wọ̀n tí mo gbé kalẹ̀ láàrín èmi àti ìwọ yìí,
52 Witness be this heap and witness be this pillar, that I will not pass by this heap, and that thou shalt not pass unto me by this heap and this pillar, for evil.
yóò jẹ́ ẹ̀rí wí pé èmi kò ni ré ọ̀wọ̀n àti òkìtì yìí kọjá láti bá ọ jà àti pé ìwọ pẹ̀lú kì yóò kọjá òkìtì tàbí ọ̀wọ̀n yìí láti ṣe mí ní ibi.
53 The God of Abraham and the God of Nachor shall judge between us, the God of their father; but Jacob swore by the Fear of his father Isaac.
Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run Abrahamu àti Ọlọ́run Nahori, àti Ọlọ́run baba wọn ṣe ìdájọ́ láàrín wa.” Jakọbu sì fi ẹ̀rù Isaaki baba rẹ̀ búra.
54 Then Jacob slew some cattle upon the mount, and called his brethren to eat bread; and they did eat bread, and tarried all night on the mount.
Jakọbu sì rú ẹbọ níbẹ̀ ni orí òkè, ó sì pe àwọn ẹbí rẹ̀ láti jẹun. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹun, ibẹ̀ náà ni wọ́n sùn ní ọjọ́ náà.
55 And early in the morning Laban rose up, and kissed his sons and his daughters and blessed them; and Laban departed, and returned unto his own place.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Labani fi ẹnu ko àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ lẹ́nu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì súre fún wọn. Labani sì padà lọ sí ilé.

< Genesis 31 >