< 2 Chronicles 7 >

1 And when Solomon had made an end of praying, a fire came down from heaven, and consumed the burnt-offering and the sacrifices; and the glory of the Lord filled the house.
Nígbà tí Solomoni sì ti parí àdúrà, iná sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó ẹbọ sísun àti ẹbọ, ògo Ọlọ́run sì kún ilé Olúwa.
2 And the priests were not able to enter into the house of the Lord; because the glory of the Lord had filled the Lord's house.
Àwọn àlùfáà kò sì le wo ilé Olúwa náà nítorí pé ògo Olúwa kún un.
3 And all the children of Israel were looking on as the fire came down, and the glory of the Lord [was resting] upon the house; and they kneeled down with their faces to the ground upon the pavement, and prostrated themselves, and gave thanks unto the Lord, for he is good; because unto everlasting endureth his kindness.
Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo Olúwa lórí ilé Olúwa náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú ni dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin Olúwa, wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa wí pé, “Nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”
4 And the king and all the people offered sacrifices before the Lord.
Nígbà náà ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn sì rú ẹbọ níwájú Olúwa.
5 And king Solomon offered a sacrifice of twenty and two thousand oxen, and a hundred and twenty thousand sheep: and so they dedicated the house of God, the king and all the people.
Ọba Solomoni sì rú ẹbọ ti ẹgbẹ̀rún méjìlélógún, orí màlúù àti àgùntàn àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn àti ẹranko. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn ya ilé Ọlọ́run sí mímọ́.
6 And the priests were standing on their stations, and the Levites with the instruments of the music of the Lord, which king David had made to give thanks unto the Lord, because unto everlasting endureth his kindness, with the song of praise of David in their hand; and the priests blew the trumpets opposite to them, and all Israel were standing.
Àwọn àlùfáà dúró ní ààyè wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi ti ṣe pẹ̀lú ohun èlò orin Olúwa, tí ọba Dafidi ti ṣe fún ìyìn Olúwa àti tí á lò nígbà tí ó dúpẹ́, wí pé, “Àánú rẹ̀ sì dúró láéláé,” níwájú àwọn ọmọ Lefi, àwọn àlùfáà sì fọn ìpè, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dúró.
7 And Solomon hallowed the interior of the court that was before the house of the Lord; for he prepared there the burnt-offerings, and the fat of the peace-offerings; because the copper altar which Solomon had made was not able to contain the burnt-offerings, and the meat-offerings, and the fat.
Solomoni sì yà àgbàlá níwájú ilé Olúwa sọ́tọ̀, níbẹ̀ sì ni ó ti ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àti ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ó ti ṣe kò lè gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọ̀rá náà.
8 And Solomon held the feast at that time seven days, and all Israel with him, a very great assembly, from the entrance of Chamath unto the river of Egypt.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àsè ní àkókò náà fún ọjọ́ méje àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ àti ìjọ ènìyàn ńlá, àwọn ènìyàn láti Lebo-Hamati títí dé odò Ejibiti.
9 And they held on the eighth day a solemn assembly; for the dedication of the altar they held seven days, and the feast seven days.
Ní ọjọ́ kẹjọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyàsímímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àsè náà fún ọjọ́ méje sí i.
10 And on the three-and-twentieth day of the seventh month he dismissed the people unto their tents, joyful and glad of heart because of the good that the Lord had done for David, and for Solomon, and for Israel his people.
Ní ọjọ́ kẹtàlélógún tí oṣù keje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi àti Solomoni, àti fún àwọn ènìyàn Israẹli.
11 Thus did Solomon complete the house of the Lord, and the king's house; and [in] all that came into Solomon's heart to make in the house of the Lord, and in his own house, he prospered.
Nígbà tí Solomoni ti parí ilé Olúwa àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé Olúwa àti nínú ilé òun tìkára rẹ̀,
12 Then appeared the Lord to Solomon during the night, and said unto him, I have heard thy prayer, and I have made choice of this place for myself as a house of sacrifice.
Olúwa sì farahàn Solomoni ní òru ó sì wí pé: “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibí yìí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.
13 If I shut up the heavens that there be no rain, or if I give a charge to the locusts to devour off the land, or if I send a pestilence among my people:
“Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma bá à sí òjò, tàbí láti pàṣẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín àwọn ènìyàn mi,
14 And if my people, over whom my name is called, do then humble themselves, and pray, and seek my presence, and turn away from their evil ways: then will I also hear from heaven, and I will forgive their sin, and will heal their land.
tí àwọn ènìyàn, tí a fi orúkọ mi pè, tí wọ́n bá rẹ ara wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì rí ojú mi, tí wọ́n sì yí kúrò nínú ọ̀nà búburú wọn, nígbà náà, èmi yóò gbọ́ láti ọ̀run, èmi yóò sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n èmi yóò sì wo ilẹ̀ wọn sàn.
15 Now, my eyes shall be open, and my ears attentive unto the prayer on this place.
Nísinsin yìí, ojú mi yóò sì là etí mi yóò sì là, sí àdúrà ọrẹ níbí yìí.
16 And now I have chosen and hallowed this house, that my name may be there for ever; and my eyes and my heart shall be there at all times.
Èmi sì ti yàn, èmi sì ti ya ilé yìí sí mímọ́ bẹ́ẹ̀ ni kí orúkọ mi kí ó le wà níbẹ̀ títí láéláé.
17 And as for thee, if thou wilt walk before me, as David thy father hath walked, so as to do in accordance with all that I have commanded thee, and wilt keep my statutes and my ordinances:
“Ní ti bí ìwọ bá rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, tí o sì ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ, tí ìwọ sì ṣe àkíyèsí àṣẹ mi láti ọ̀run,
18 Then will I establish the throne of thy kingdom, just as I have covenanted with David thy father, saying, There shall never fail thee a man to be ruler in Israel.
Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe pẹ̀lú Dafidi baba rẹ nígbà tí mo bá a dá májẹ̀mú wí pé, ìwọ kò ní fẹ́ ẹnìkan kù láti ṣe alákòóso lórí Israẹli.
19 But if ye will indeed turn away, and forsake my statutes and my commandments, which I have set before you, and will go and serve other gods, and bow down to them:
“Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá yípadà tí o sì kọ òfin mi sílẹ̀ àti àṣẹ tí mo ti fi fún yín tí ẹ sì lọ sókè láti lọ sin ọlọ́run mìíràn tí ẹ sì bọ wọ́n,
20 Then will I pluck them up out of my land which I have given unto them; and this house, which I have hallowed for my name, will I cast away from my sight, and I will render it to be for a proverb and for a by-word among all the people.
nígbà náà ni èmi yóò fa Israẹli tu kúrò láti ilẹ̀ mi, èyí tí èmi ti fi fún wọn, èmi yóò sì kọ̀ ilé náà sílẹ̀ èyí tí èmi ti yà sọ́tọ̀ fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ṣe ọ̀rọ̀ òwe, n ó fi ṣe ẹlẹ́yà láàrín gbogbo ènìyàn,
21 And this house, which hath been so exalted, shall become an astonishment to every one that passeth by it: so that he will say, Why hath the Lord done thus unto this land, and unto this house?
àti ní gbogbo àyíká ilé yìí nísinsin yìí, bẹ́ẹ̀ ni yóò di ohun ìtànjẹ; gbogbo àwọn tí ó bá sì kọjá níbẹ̀ ni yóò jáláyà, wọn yóò sì wí pé, ‘Kí ni ó dé tí Olúwa fì ṣe irú èyí sí ilẹ̀ yí àti sí ilé yìí?’
22 And men shall then say, For the cause that they forsook the Lord the God of their fathers, who had brought them forth out of the land of Egypt, and they took hold of other gods, and bowed down to them, and served them: therefore hath he brought upon them all this evil.
Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run baba wọn ẹni tí ó mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti fi ọwọ́ gba ọlọ́run mìíràn mọ́ra, wọ́n bọ wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyí tí ó fi mú gbogbo ìjàǹbá náà wá sórí wọn.’”

< 2 Chronicles 7 >