< 2 Chronicles 24 >

1 Seven years old was Joash when he became king, and forty years did he reign in Jerusalem: and the name of his mother was Zibyah of Beer-sheba'.
Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
2 And Joash did what is right in the eyes of the Lord, all the days of Yehoyada' the priest.
Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
3 And Yehoyada' took for himself two wives, and he begat sons and daughters.
Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
4 And it came to pass after this, that Yoash had it in his mind to renew the house of the Lord.
Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
5 And he gathered together the priests and the Levites, and said to them, Go out unto the cities of Judah, and gather from all Israel money to repair the house of your God from year to year, and ye shall make haste in this matter. But the Levites made no haste.
Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
6 Then called the king for Yehoyada' the chief, and said unto him, Why hast thou not required from the Levites to bring in out of Judah and out of Jerusalem the contribution [fixed by] Moses the servant of the Lord, and of the congregation of Israel, for the tabernacle of the testimony?
Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
7 For the sons of the wicked 'Athalyahu have made breaches [in] the house of God; and also the holy things of the house of the Lord have they applied to the Be'alim.
Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
8 And at the king's order they made a chest, and placed it at the gate of the house of the Lord on the outside.
Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
9 And they made a proclamation through Judah and Jerusalem, to bring in to the Lord the contribution [fixed by] Moses the servant of God upon Israel in the wilderness.
A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
10 And all the princes and all the people rejoiced, and they brought it in, and cast it into the chest, until it was full.
Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
11 Now it came to pass, that at what time the chest was brought unto the king's office by the hand of the Levites, and when they saw that there was much money, then came the king's scribe and the high-priest's officer and emptied the chest, and took it up, and brought it back to its place. Thus did they day by day, and gathered money in abundance.
Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
12 And the king and Yehoyada' gave it to those who overlooked the service of the house of the Lord, and these hired masons and carpenters to renew the house of the Lord, and also to the workers in iron and copper to repair the house of the Lord.
Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
13 So the workmen wrought, and the work was restored through their means, and they replaced the house of God in its [former] state, and strengthened it.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
14 And when they had completed it, they brought before the king and Yehoyada' the rest of the money, and they made of it vessels for the house of the Lord, the vessels of the service and for the sacrificing, and the spoons, and [other] vessels of gold and silver. And they offered burnt-offerings in the house of the Lord continually all the days of Yehoyada'.
Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
15 And Yehoyada' became old, and was full of days, and died: he was old one hundred and thirty years when he died.
Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
16 And they buried him in the city of David among the kings; because he had done a good thing in Israel, and toward God, and his house.
Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
17 But after the death of Yehoyada' came the princes of Judah, and bowed themselves down to the king. Then did the king hearken unto them.
Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
18 And they forsook the house of the Lord the God of their fathers, and served the Asherim and the idols: and there came wrath over Judah and Jerusalem for this their guiltiness.
Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
19 And he sent prophets among them, to bring them back again unto the Lord; and they gave them warning; but they did not give ear.
Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
20 And the spirit of God endued Zechariah the son of Yehoyada' the priest, and he stood up above the people, and he said unto them, Thus hath said the [true] God, Why transgress ye the commandments of the Lord? ye cannot prosper so; because [as] ye have forsaken the Lord, he hath also forsaken you.
Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’”
21 And they conspired against him, and stoned him with stones at the command of the king in the court of the house of the Lord.
Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
22 And king Joash did not remember the kindness which Yehoyada' his father had shown to him, but slew his son. And when he died, he said, The Lord will see [this], and require [my blood].
Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
23 And it came to pass at the expiration of the year, that the army of Syria came up against him: and they came to Judah and Jerusalem, and destroyed all the princes of the people from among the people, and all their spoil they sent off unto the king of Damascus.
Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
24 Indeed with a small company of men did the army of Syria come; but the Lord delivered into their hand an army exceedingly numerous; because they had forsaken the Lord the God of their fathers. And on Joash they executed punishment.
Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
25 And when these were gone away from him—for they left him [suffering] with great diseases—his own servants conspired against him because of the blood of the sons of Yehoyada' the priest, and slew him on his bed, and he died: and they buried him in the city of David, but they buried him not in the sepulchres of the kings.
Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
26 And these are those that conspired against him; Zabad the son of Shim'ath the 'Ammonitess, and Yehozabad the son of Shimrith the Moabitess.
Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
27 Now concerning his sons, and the great prophecy concerning him, and the founding of the house of God, behold, they are written in the story of the book of the kings. And Amazyahu his son became king in his stead.
Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< 2 Chronicles 24 >