< 2 Chronicles 15 >
1 And as for 'Azaryahu the son of 'Oded—on him came the spirit of God;
Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
2 And he went out to meet Assa, and said unto him, Hear me, O Assa, and all Judah and Benjamin, The Lord is with you, while ye remain with him; and if ye seek him, he will let himself be found by you; but if ye forsake him, he will forsake you.
Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
3 And many days [had elapsed] for Israel, [they being] without the true God, and without a teaching priest, and without law.
Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
4 But they returned when they were in distress unto the Lord, the God of Israel, and they sought him, and he let himself be found by them.
Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
5 And in those times there was no peace to him that went out, and to him that came in; but there were great confusions among all the inhabitants of the countries.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
6 And nation was dashed to pieces against nation, and city against city; for God did confound them with all kind of distress.
Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
7 But as for you, be ye strong, and let not your hands be weak; for there is a reward for your doing.
Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
8 And when Assa heard these words, and the prophecy of 'Oded the prophet, he was strengthened, and he put away the abominable idols out of all the land of Judah and Benjamin, and out of the cities which he had captured from the mountain of Ephraim; and he renewed the altar of the Lord, that was before the porch of the Lord.
Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
9 And he assembled all Judah and Benjamin, and those that sojourned with them out of Ephraim and Menasseh, and out of Simeon; for they had joined him out of Israel in abundance, when they saw that the Lord his God was with him.
Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 And so they assembled themselves at Jerusalem in the third month, in the fifteenth year of the reign of Assa.
Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
11 And they sacrificed unto the Lord on the same day, of the booty which they had brought, seven hundred oxen and seven thousand sheep.
Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
12 And they entered into the covenant to seek the Lord the God of their fathers with all their heart and with all their soul;
Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
13 So that whosoever would not seek the Lord the God of Israel should be put to death, from the small even up to the great, whether it be man or woman.
Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
14 And they swore unto the Lord with a loud voice, and with [joyful] shouting, and with trumpets, and with cornets.
Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
15 And all Judah rejoiced because of the oath; for with all their heart had they sworn, and with their whole desire did they seek him, and he let himself be found by them: and the Lord gave them rest on every side.
Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
16 And also concerning Ma'achah the mother of king Assa, he removed her from being queen, because she had made a scandalous image for the grove; and Assa cut down her scandalous image, and had it ground up, and burnt it by the brook Kidron.
Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
17 But the high-places were not removed out of Israel; nevertheless the heart of Assa was entire all his days.
Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
18 And be brought the things which his father had sanctified, and his own sanctified things, into the house of God, —silver, and gold, and vessels.
Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
19 And there was no war until the five-and-thirtieth year of the reign of Assa.
Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.