< 1 Kings 15 >

1 Now in the eighteenth year of king Jerobo'am the son of Nebat became Abiyam king over Judah.
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
2 Three years he reigned in Jerusalem. And his mother's name was Ma'achah, the daughter of Abishalom.
ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
3 And he walked in all the sins of his father, which he had done before him; and his heart was not entire with the Lord his God, like the heart of David his father.
Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
4 Nevertheless for the sake of David did the Lord his God give him a rule in Jerusalem, to set up his son after him, and to allow Jerusalem to exist.
Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
5 Because David did what is right in the eyes of the Lord, and turned not aside from all that he had commanded him all the days of his life, save only in the matter of Uriyah the Hittite.
Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
6 And there had been war between Rehobo'am and Jerobo'am all the days of his life.
Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
7 And the rest of the acts of Abiyam, and all that he did, behold, they are written in the book of the chronicles of the kings of Judah. And there was [also] war between Abiyam and Jerobo'am.
Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
8 And Abiyam slept with his fathers; and they buried him in the city of David: and Assa his son became king in his stead.
Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
9 And in the twentieth year of Jerobo'am the king of Israel became Assa king over Judah.
Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
10 And forty and one years did he reign in Jerusalem. And the name of his mother was Ma'achah, the daughter of Abishalom.
Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
11 And Assa did what is right in the eyes of the Lord, like David his father.
Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
12 And he put away the sodomites out of the land, and removed all the idols which his fathers had made.
Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
13 And also Ma'achah his mother, even her he removed from being queen; because she had made a scandalous image for the grove; and Assa cut down her scandalous image, and burnt it by the brook Kidron.
Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
14 But the high-places were not removed; nevertheless Assa's heart was entire with the Lord all his days.
Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
15 And he brought the things which his father had sanctified, and his own sanctified things, into the house of the Lord, silver, and gold, and vessels.
Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
16 And there was war between Assa and Ba'sha the king of Israel all their days.
Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
17 And Ba'sha the king of Israel went up against Judah, and built Ramah, in order not to suffer any one to go out or come in to Assa the king of Judah.
Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
18 Then did Assa take all the silver and the gold that were left in the treasures of the house of the Lord, and the treasures of the king's house, and gave them into the hand of his servants; and king Assa sent them to Ben-hadad, the son of Tabrimmon, the son of Chesyon, the king of Syria, who dwelt in Damascus, saying,
Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
19 A covenant is between me and thee, [as] between my father and thy father: behold, I have sent unto thee a present of silver and gold; go and do break thy covenant with Ba'sha the king of Israel, that he may withdraw from me.
Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
20 And Ben-hadad hearkened unto king Assa, and sent the captains of the armies which he had against the cities of Israel, and smote 'Iyon, and Dan, and Abel-beth-ma'achah, and the whole of Kinneroth, with all the land of Naphtali.
Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
21 And it came to pass, when Ba'sha heard this, that he left off the building of Ramah, and remained in Tirzah.
Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
22 Then king Assa called together by proclamation all Judah, none being exempted: and they took away the stones of Ramah, and its timber, wherewith Ba'sha had built; and king Assa built with them Geba' of Benjamin, and Mizpah.
Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
23 And the rest of all the acts of Assa, and all his mighty deeds, and all that he did, and the cities which he built, behold, they are written in the book of the chronicles of the kings of Judah. Nevertheless in the time of his old age he became diseased in his feet.
Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
24 And Assa slept with his fathers, and was buried with his fathers in the city of David his father: and Jehoshaphat his son became king in his stead.
Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
25 And Nadab the son of Jerobo'am became king over Israel in the second year of Assa the king of Judah; and he reigned over Israel two years.
Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
26 And he did what is evil in the eyes of the Lord, and he walked in the way of his father, and in his sin wherewith he had induced Israel to sin.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
27 And Ba'sha the son of Achiyah, of the house of Issachar, conspired against him; and Ba'sha smote him at Gibbethon, which belonged to the Philistines: while Nadab and all Israel were besieging Gibbethon.
Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
28 And Ba'sha slew him in the third year of Assa the king of Judah, and became king in his stead.
Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 And it came to pass, when he reigned, that he smote all the house of Jerobo'am; he left not any that breathed unto Jerobo'am, until he had destroyed him, according to the word of the Lord, which he had spoken by his servant Achiyah the Shilonite;
Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
30 Because of the sins of Jerobo'am which he had sinned, and through which he had induced Israel to sin, by his provoking wherewith he provoked the Lord the God of Israel to anger.
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
31 And the rest of the acts of Nadab, and all that he did, behold, they are written in the book of the chronicles of the kings of Israel.
Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
32 And there was war between Assa and Ba'sha the king of Israel all their days.
Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
33 In the third year of Assa the king of Judah became Ba'sha the son of Achiyah king over all Israel, in Thirzah, [for] twenty and four years.
Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
34 And he did what is evil in the eyes of the Lord, and walked in the way of Jerobo'am, and in his sin wherewith he had induced Israel to sin.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.

< 1 Kings 15 >