< 1 Chronicles 2 >

1 These are the sons of Israel: Reuben, Simeon, Levi, and Judah, Issachar, and Zebulun,
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
2 Dan, Joseph, and Benjamin, Naphtali, Gad, and Asher.
Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
3 The sons of Judah: 'Er, and Onan, and Shelah, the three [who] were born unto him of the daughter of Shua' the Canaanitess. And 'Er, the first-born of Judah, was evil in the eyes of the Lord: and he slew him.
Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
4 And Thamar his daughter-in-law bore unto him Perez and Zerach. All the sons of Judah were five.
Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
5 The sons of Perez: Chezron and Chamul.
Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
6 And the sons of Zerach: Zimri, and Ethan, and Heman, and Calcol, and Dara'; all of them five.
Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
7 And the sons of Carmi: 'Achar the troubler of Israel, who trespassed against the devoted things.
Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
8 And the sons of Ethan: 'Azaryah.
Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
9 And the sons of Chezron, that were born unto him: Jerachmeel, and Ram, and Kelubai.
Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
10 And Ram begat 'Amminadab, and 'Amminadab begat Nachshon, the prince of the children of Judah;
Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
11 And Nachshon begat Salma, and Salma begat Bo'az,
Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
12 And Bo'az begat 'Obed, and 'Obed begat Jesse,
Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
13 And Ishai begat his first-born Eliab, and Abinadab the second, and Shim'a the third,
Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
14 Nathanel the fourth, Raddai the fifth,
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
15 Ozem the sixth, David the seventh;
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
16 And their sisters were Zeruyah, and Abigayil. And the sons of Zeruyah: Abshai, and Joab, and 'Assahel, three.
Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
17 And Abigayil bore 'Amassa: and the father of 'Amassa was Jether the Ishme'elite.
Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
18 And Caleb the son of Chezron begat [children] of 'Azubah his wife, and of Jeri'oth; and these are her sons: Jesher, and Shobab, and Ardon.
Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
19 And 'Azubah died, when Caleb took unto himself Ephrath, who bore unto him Chur.
Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
20 And Chur begat Uri, and Uri begat Bezalel.
Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
21 And afterward came Chezron to the daughter of Machir the father of Gil'ad, and he took her [for wife] when he was sixty years old: and she bore unto him Segub.
Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
22 And Segub begat Jair, who had three and twenty cities in the land of Gil'ad.
Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
23 But Geshur and Aram took the small towns of Jair from them, with Kenath, and the villages thereof, even sixty cities. All these [belonged to] the sons of Machir the father of Gil'ad.
(Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
24 And after Chezron was dead in Calebephratah, then bore Chezron's wife Abiyah unto him Ashchur the father of Thekoa'.
Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
25 And the sons of Jerachmeel the first-born of Chezron were, Ram the first-born, and Bunah, and Oren, and Ozem, and Achiyah.
Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
26 Yerachmeel had also another wife, whose name was 'Atarah; she was the mother of Onam.
Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
27 And the sons of Ram the first-born of Jerachmeel were, Ma'az, and Jamin, and 'Eker.
Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
28 And the sons of Onam were, Shammai, and Jada'. And the sons of Shammai: Nadab, and Abishur.
Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
29 And the name of the wife of Abishur was Abichayil, and she bore unto him Achban, and Molid.
Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
30 And the sons of Nadab: Seled, and Appayim; and Seled died without children.
Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
31 And the sons of Appayim: Yish'i. And the sons of Yish'i: Sheshan. And the sons of Sheshan: Achlai.
Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
32 And the sons of Jada' the brother of Shammai: Jether, and Jonathan; and Jether died without children.
Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
33 And the sons of Jonathan: Peleth, and Zaza. These were the sons of Jerachmeel.
Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
34 Now Sheshan had no sons, but daughters. And Sheshan had a servant, an Egyptian, whose name was Jarcha'.
Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
35 And Sheshan gave his daughter unto Jarcha' his servant for wife: and she bore unto him 'Attai.
Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
36 And 'Attai begat Nathan, and Nathan begat Zabad.
Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
37 And Zabad begat Ephlal, and Ephlal begat 'Obed.
Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
38 And 'Obed begat Jehu, and Jehu begat 'Azaryah,
Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
39 And 'Azaryah begat Chelez, and Chelez begat El'assah,
Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
40 And El'assah begat Sissmai, and Sissmai begat Shallum.
Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
41 And Shallum begat Jekamyah, and Jekamyah begat Elishama'.
Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
42 Now the sons of Caleb the brother of Jerachmeel were, Mesha', his first-born, who was the father of Ziph, and of the sons of Mareshah the father of Hebron.
Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
43 And the sons of Hebron: Korach, and Thappuach, and Rekem, and Shema'.
Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
44 And Shema' begat Racham, the father of Jorke'am; and Rekem begat Shammai.
Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
45 And the son of Shammai was Ma'on; and Ma'on was the father of Beth-zur.
Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
46 And 'Ephah, Caleb's concubine, bore Charan, and Moza, and Gazez; and Charan begat Gazez.
Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
47 And the sons of Jahdai: Regem, and Jotham, and Gesham, and Pelet, and 'Ephah, and Sha'aph.
Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
48 Ma'achah, Caleb's concubine, bore Sheber, and Tirchanah.
Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
49 She bore also! Sha'aph the father of Madmannah. Sheva the father of Machbena, and the father of Gib'a: ! and the daughter of Caleb was 'Achsah.
Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
50 These were the sons of Caleb: Benchur, the first-born of Ephratah, Shobal the father of Kiryath-ye'arim,
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
51 Salma the father of Beth-lechem, Chareph the father of Beth-gader.
Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
52 And Shobal the father of Kir'yath-ye'arim had sons: Haroeh, and Chazi-hammenuchoth.
Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
53 And the families of Kir'yath-ye'arim are the Yithrites, and the Puthites, and the Shumathites, and the Mishra'ites: from these came the Zor'athites, and the Eshthaulites.
Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
54 The sons of Salma: Beth-lechem, and the Netophathites, 'Ataroth of the house of Joab, and Chazi-hammanachthi, the Zor'ite.
Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
55 And the families of the scribes who dwelt at Jabez: the Thirathites, the Shim'athites, and Suchathites. These are the Kenites that came from Chammath, the father of the house of Rechab.
àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.

< 1 Chronicles 2 >