< Psalms 65 >
1 For the end, a Psalm [and] Song of David. Praise becomes you, O God, in Sion; and to you shall the vow be performed.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Orin. Ìyìn ń dúró dè ọ́, Ọlọ́run, ní Sioni; sí ọ ni a ó mú ẹ̀jẹ́ wa ṣẹ.
2 Hear my prayer; to you all flesh shall come.
Ìwọ tí ó ń gbọ́ àdúrà, gbogbo ènìyàn yóò sì wá sọ́dọ̀ rẹ.
3 The words of transgressors have overpowered us; but do you pardon our sins.
Ọ̀ràn àìṣedéédéé borí mi bí ó ṣe ti ìrékọjá wa ni! Ìwọ ni yóò wẹ̀ wọ́n nù kúrò.
4 Blessed [is he] whom you have chosen and adopted; he shall dwell in your courts; we shall be filled with the good things of your house; your temple is holy.
Ìbùkún ni fún àwọn tí o yàn tí o mú wa láti máa gbé àgọ́ rẹ! A tẹ́ wá lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere inú ilé rẹ, ti tẹmpili mímọ́ rẹ.
5 [You are] wonderful in righteousness. Listen to us, O God our Saviour; the hope of all the ends of the earth, and of them [that are] on the sea afar off:
Ìwọ dá wa lóhùn pẹ̀lú ohun ìyanu ti òdodo, Ọlọ́run olùgbàlà wa, ẹni tí ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé gbogbo òpin ayé àti àwọn tí ó jìnnà nínú òkun,
6 who do establish the mountains in your strength, being girded about with power;
ìwọ tí ó dá òkè nípa agbára rẹ, tí odi ara rẹ ní àmùrè agbára,
7 who trouble the depth of the sea, the sounds of its waves.
ẹni tí ó mú rírú omi òkun dákẹ́, ríru ariwo omi wọn, àti ìdágìrì àwọn ènìyàn.
8 The nations shall be troubled, and they that inhabit the ends [of the earth] shall be afraid of your signs; you will cause the outgoings of morning and evening to rejoice.
Àwọn tí ó ń gbé òkèrè bẹ̀rù, nítorí àmì rẹ wọ̀n-ọn-nì; ìwọ mú ìjáde òwúrọ̀ àti ti àṣálẹ́ yọ̀, ìwọ pè fún orin ayọ̀.
9 You have visited the earth, and saturated it; you have abundantly enriched it. The river of God is filled with water; you have prepared their food, for thus is the preparation [of it].
Ìwọ bẹ ayé wò, o sì bomirin; ìwọ mú un ọ̀rọ̀ púpọ̀. Odò Ọlọ́run kún fún omi láti pèsè ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ibẹ̀ ni ìwọ ti yàn án.
10 Saturate her furrows, multiply her fruits; [the crop] springing up shall rejoice in its drops.
Ìwọ fi bomirin sí aporo rẹ̀ ìwọ tẹ́ ògúlùtu rẹ̀; ìwọ fi òjò mú ilẹ̀ rẹ̀ rọ̀, o sì bùkún ọ̀gbìn rẹ̀.
11 You will bless the crown of the year [because] of your goodness; and your plains shall be filled with fatness.
Ìwọ fi oore rẹ dé ọdún ní adé, ọ̀rá ń kán ní ipa ọ̀nà rẹ.
12 The mountains of the wilderness shall be enriched; and the hills shall gird themselves with joy.
Pápá tútù ní aginjù ń kan àwọn òkè kéékèèké fi ayọ̀ di ara wọn ní àmùrè.
13 The rams of the flock are clothed [with wool], and the valleys shall abound in corn; they shall cry aloud, yes they shall sing hymns.
Agbo ẹran ni a fi wọ pápá tútù náà ní aṣọ; àfonífojì ni a fi ọkà bò mọ́lẹ̀, wọ́n hó fún ayọ̀, wọ́n ń kọrin pẹ̀lú.