< Psalms 147 >
1 Alleluia, [a Psalm] of Aggaeus and Zacharias. Praise you the Lord: for psalmody is a good thing; let praise be sweetly sung to our God.
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa, ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
2 The Lord builds up Jerusalem; and he will gather together the dispersed of Israel.
Olúwa kọ́ Jerusalẹmu; Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
3 He heals the broken in heart, and binds up their wounds.
Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
4 He numbers the multitudes of stars; and calls them all by names.
Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
5 Great is our Lord, and great is his strength; and his understanding is infinite.
Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
6 The Lord lifts up the meek; but brings sinners down to the ground.
Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
7 Begin [the song] with thanksgiving to the Lord; sing praises on the harp to our God:
Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
8 who covers the heaven with clouds, who prepares rain for the earth, who causes grass to spring up on the mountains, [[and green herb for the service of men; ]]
Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
9 and gives cattle their food, and to the young ravens that call upon him.
Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
10 He will not take pleasure in the strength of a horse; neither is he well-pleased with the legs of a man.
Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
11 The Lord takes pleasure in them that fear him, and in all that hope in his mercy.
Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
12 Alleluia, a Psalm of Aggaeus and Zacharias. Praise the Lord, O Jerusalem; praise your God, O Sion.
Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu; yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
13 For he has strengthened the bars of your gates; he has blessed your children within you.
Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára, Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
14 He makes your borders peaceful, and fills you with the flour of wheat.
Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
15 He sends his oracle to the earth: his word will run swiftly.
Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
16 He gives snow like wool: he scatters the mist like ashes.
Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
17 Casting [forth] his ice like morsels: who shall stand before his cold?
Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
18 He shall send out his word, and melt them: he shall blow [with] his wind, and the waters shall flow.
Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́ ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
19 He sends his word to Jacob, his ordinances and judgments to Israel.
Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
20 He has not done so to any [other] nation; and he has not shown them his judgments.
Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀ wọn ko mọ òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.