< Numbers 33 >

1 And these are the stages of the children of Israel, as they went out from the land of Egypt with their host by the hand of Moses and Aaron.
Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
2 And Moses wrote their removals and their stages, by the word of the Lord: and these are the stages of their journeying.
Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
3 They departed from Ramesses in the first month, on the fifteenth day of the first month; on the day after the passover the children of Israel went forth with a high hand before all the Egyptians.
Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
4 And the Egyptians buried those that died of them, even all that the Lord struck, every firstborn in the land of Egypt; also the Lord executed vengeance on their gods.
Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
5 And the children of Israel departed from Ramesses, and encamped in Socchoth:
Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
6 and they departed from Socchoth and encamped in Buthan, which is a part of the wilderness.
Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
7 And they departed from Buthan and encamped at the mouth of Iroth, which is opposite Beel-sepphon, and encamped opposite Magdol.
Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
8 And they departed from before Iroth, and crossed the middle of the sea into the wilderness; and they went a journey of three days through the wilderness, and encamped in Picriae.
Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
9 And they departed from Picriae, and came to Aelim; and in Aelim [were] twelve fountains of water, and seventy palm-trees, and they encamped there by the water.
Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
10 And they departed from Aelim, and encamped by the Red Sea.
Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
11 And they departed from the Red Sea, and encamped in the wilderness of Sin.
Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
12 And they departed from the wilderness of Sin, and encamped in Raphaca.
Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
13 And they departed from Raphaca, and encamped in Aelus.
Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
14 And they departed from Aelus, and encamped in Raphidin; and there was no water there for the people to drink.
Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
15 And they departed from Raphidin, and encamped in the wilderness of Sina.
Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
16 And they departed from the wilderness of Sina, and encamped at the Graves of Lust.
Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
17 And they departed from the Graves of Lust, and encamped in Aseroth.
Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
18 And they departed from Aseroth, and encamped in Rathama.
Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
19 And they departed from Rathama, and encamped in Remmon Phares.
Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
20 And they departed from Remmon Phares, and encamped in Lebona.
Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
21 And they departed from Lebona, and encamped in Ressan.
Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
22 And they departed from Ressan, and encamped in Makellath.
Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
23 And they departed from Makellath, and encamped in Saphar.
Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
24 And they departed from Saphar, and encamped in Charadath.
Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
25 And they departed from Charadath, and encamped in Makeloth.
Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
26 And they departed from Makeloth, and encamped in Kataath.
Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
27 And they departed from Kataath, and encamped in Tarath.
Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
28 And they departed from Tarath, and encamped in Mathecca.
Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
29 And they departed from Mathecca, and encamped in Selmona.
Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
30 And they departed from Selmona, and encamped in Masuruth.
Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
31 And they departed from Masuruth, and encamped in Banaea.
Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
32 And they departed from Banaea, and encamped in the mountain Gadgad.
Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
33 And they departed from the mountain Gadgad, and encamped in Etebatha.
Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
34 And they departed from Etebatha, and encamped in Ebrona.
Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
35 And they departed from Ebrona, and encamped in Gesion Gaber.
Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
36 And they departed from Gesion Gaber, and encamped in the wilderness of Sin; and they departed from the wilderness of Sin, and encamped in the wilderness of Pharan; this is Cades.
Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
37 And they departed from Cades, and encamped in mount Or near the land of Edom.
Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
38 And Aaron the priest went up by the command of the Lord, and died there in the forties year of the departure of the children of Israel from the land of Egypt, in the fifth month, on the first [day] of the month.
Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
39 And Aaron was a hundred and twenty-three years old, when he died in mount Or.
Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
40 And Arad the Chananitish king (he too lived in the land of Chanaan) having heard when the children of Israel were entering [the land]—
Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
41 then they departed from mount Or, and encamped in Selmona.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
42 And they departed from Selmona, and encamped in Phino.
Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
43 And they departed from Phino, and encamped in Oboth.
Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
44 And they departed from Oboth, and encamped in Gai, on the other side [Jordan] on the borders of Moab.
Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
45 And they departed from Gai, and encamped in Daebon Gad.
Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
46 And they departed from Daebon Gad, and encamped in Gelmon Deblathaim.
Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
47 And they departed from Gelmon Deblathaim, and encamped on the mountains of Abarim, over against Nabau.
Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
48 And they departed from the mountains of Abarim, and encamped on the west of Moab, at Jordan by Jericho.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
49 And they encamped by Jordan between Aesimoth, as far as Belsa to the west of Moab.
Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
50 And the Lord spoke to Moses at the west of Moab by Jordan at Jericho, saying,
Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
51 Speak to the children of Israel, and you shall say to them, You are to pass over Jordan into the land of Chanaan.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
52 And you shall destroy all that dwell in the land before your face, and you shall abolish their high places, and all their molten images you shall destroy, and you shall demolish all their pillars.
lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
53 And you shall destroy all the inhabitants of the land, and you shall dwell in it, for I have given their land to you for an inheritance.
Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
54 And you shall inherit their land according to your tribes; to the greater number you shall give the larger possession, and to the smaller you shall give the less possession; to whatever [part] a man's name shall go forth [by lot], there shall be his [property]: you shall inherit according to the tribes of your families.
Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
55 But if you will not destroy the dwellers in the land from before you, then it shall come to pass that whoever of them you shall leave shall be thorns in your eyes, and darts in your sides, and they shall be enemies to you on the land on which you shall dwell;
“‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
56 and it shall come to pass that as I had determined to do to them, so I will do to you.
Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”

< Numbers 33 >