< Nehemiah 7 >
1 And it came to pass, when the wall was built, and I had set up the doors, and the porters and the singers and the Levites were appointed,
Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
2 that I gave charge to Ananias my brother, and Ananias the ruler of the palace, over Jerusalem: for he was a true man, and one that feared God beyond many.
Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
3 And I said to them, The gates of Jerusalem shall not be opened till sunrise; and while they are still watching, let the doors be shut, and bolted; and set watches of them that dwell in Jerusalem, [every] man at his post, and [every] man over against his house.
Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
4 Now the city [was] wide and large; and the people [were] few in it, and the houses were not built.
Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
5 And God put [it] into my heart, and I gathered the nobles, and the rulers, and the people, into companies: and I found a register of the company that came up first, and I found written in it as follows:
Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
6 Now these [are] the children of the country, that came up from captivity, of the number which Nabuchodonosor king of Babylon carried away, and they returned to Jerusalem and to Juda, [every] man to his city;
Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
7 with Zorobabel, and Jesus, and Neemia, Azaria, and Reelma, Naemani, Mardochaeus, Balsan, Maspharath, Esdra, Boguia, Inaum, Baana, Masphar, men of the people of Israel.
Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
8 The children of Phoros, two thousand one hundred and seventy-two.
àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
9 The children of Saphatia, three hundred and seventy-two.
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
10 The children of Era, six hundred and fifty-two.
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
11 The children of Phaath Moab, with the children of Jesus and Joab, two thousand six hundred and eighteen.
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
12 The children of Aelam, a thousand two hundred and fifty-four.
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
13 The children of Zathuia, eight hundred and forty-five.
Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
14 The children of Zacchu, seven hundred and sixty.
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
15 The children of Banui, six hundred and forty-eight.
Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
16 The children of Bebi, six hundred and twenty-eight.
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
17 The children of Asgad, two thousand three hundred and twenty-two.
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
18 The children of Adonicam, six hundred and sixty-seven.
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
19 The children of Bagoi, two thousand and sixty-seven.
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
20 The children of Edin, six hundred and fifty-five.
Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
21 The children of Ater, [the son] of Ezekias, ninety-eight.
Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
22 The children of Esam, three hundred and twenty-eight.
Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
23 The children of Besei, three hundred and twenty-four.
Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
24 The children of Ariph, a hundred and twelve: the children of Asen, two hundred and twenty-three.
Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
25 The children of Gabaon, ninety-five.
Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
26 The children of Baethalem, a hundred and twenty-three: the children of Atopha, fifty-six.
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
27 The children of Anathoth, a hundred and twenty-eight.
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
28 The men of Bethasmoth, forty-two.
Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
29 The men of Cariatharim, Caphira, and Beroth, seven hundred and forty-three.
Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
30 The men of Arama and Gabaa, six hundred and twenty.
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
31 The men of Machemas, a hundred and twenty-two.
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
32 The men of Baethel and Ai, a hundred and twenty-three.
Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
33 The men of Nabia, a hundred an fifty-two.
Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
34 The men of Elamaar, one thousand two hundred and fifty-two.
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
35 The children of Eram, three hundred and twenty.
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
36 The children of Jericho, three hundred and forty-five.
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
37 The children of Lodadid and Ono, seven hundred and twenty-one.
Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
38 The children of Sanana, three thousand nine hundred and thirty.
Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
39 The priests; the sons of Jodae, [pertaining] to the house of Jesus, nine hundred and seventy-three.
Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
40 The children of Emmer, one thousand and fifty-two.
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
41 The children of Phaseur, one thousand two hundred and forty-seven.
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
42 The children of Eram, a thousand and seventeen.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
43 The Levites; the children of Jesus the son of Cadmiel, with the children of Uduia, seventy-four.
Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
44 The singers; the children of Asaph, a hundred and forty-eight.
Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
45 The porters; the children of Salum, the children of Ater, the children of Telmon, the children of Acub, the children of Atita, the children of Sabi, a hundred and thirty-eight.
Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
46 The Nathinim; the children of Sea, the children of Aspha, the children of Tabaoth,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
47 the children of Kiras, the children of Asuia, the children of Phadon,
Kerosi, Sia, Padoni,
48 the children of Labana, the children of Agaba, the children of Selmei,
Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
49 the children of Anan, the children of Gadel, the children of Gaar,
Hanani, Giddeli, Gahari,
50 the children of Raaia, the children of Rasson, the children of Necoda,
Reaiah, Resini, Nekoda,
51 the children of Gezam, the children of Ozi, the children of Phese,
Gassamu, Ussa, Pasea,
52 the children of Besi, the children of Meinon, the children of Nephosasi,
Besai, Mehuni, Nefisimu,
53 the children of Bacbuc, the children of Achipha, the children of Arur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri,
54 the children of Basaloth, the children of Mida, the children of Adasan,
Basluti, Mehida, Harṣa,
55 the children of Barcue, the children of Sisarath, the children of Thema,
Barkosi, Sisera, Tema,
56 the children of Nisia, the children of Atipha.
Nesia, àti Hatifa.
57 The children of the servants of Solomon; the children of Sutei, the children of Sapharat, the children of Pherida,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
58 the children of Jelel, the children of Dorcon, the children of Gadael,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
59 the children of Saphatia, the children of Ettel, the children of Phacarath, the children of Sabaim, the children of Emim.
Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
60 All the Nathinim, and children of the servants of Solomon, [were] three hundred and ninety-two.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
61 And these went up from Thelmeleth, Thelaresa, Charub, Eron, Jemer: but they could not declare the houses of their families, or their seed, whether they were of Israel.
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
62 The children of Dalaia, the children of Tobia, the children of Necoda, six hundred and forty-two.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
63 And of the priests; the children of Ebia, the children of Acos, the children of Berzelli, for they took wives of the daughters of Berzelli the Galaadite, and they were called by their name.
Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
64 These sought the pedigree of their company, and it was not found, and they were removed [as polluted] from the priesthood.
Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
65 And the Athersastha said, that they should not eat of the most holy things, until a priest should stand up to give light.
Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
66 And all the congregation was about forty-two thousand three hundred and sixty,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
67 besides their menservants and their maidservants: these were seven thousand three hundred and thirty seven: and the singing-men and singing-women, two hundred and forty-five.
yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 Two thousand seven hundred asses.
ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
70 And part of the heads of families gave into the treasury to Neemias for the work a thousand pieces of gold, fifty bowls, and thirty priests' [garments].
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
71 And [some] of the heads of families gave into the treasuries of the work, twenty thousand pieces of gold, and two thousand three hundred pounds of silver.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
72 And the rest of the people gave twenty thousand pieces of gold, and two thousand two hundred pounds of silver, and sixty-seven priests' [garments].
Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
73 And the priests, and Levites, and porters, and singers, and [some] of the people, and the Nathinim, and all Israel, lived in their cities.
Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,