< Jezekiel 15 >

1 And the word of the Lord came to me, saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2 And you, son of man—of all the wood, of the branches that are among the trees of the forest, what shall be made of the wood of the vine?
“Ọmọ ènìyàn, báwo ni igi àjàrà ṣe dára ju igi mìíràn lọ tàbí jù ẹ̀ka àjàrà tó wà láàrín igi yòókù nínú igbó?
3 Will they take wood of it to make [it fit] for work? will they take of it a peg to hang any vessel upon it?
Ǹjẹ́ a wa lè mú igi lára rẹ̀ ṣe nǹkan tí ó wúlò bí? Tàbí kí ènìyàn fi ṣe èèkàn tí yóò fi nǹkan kọ́?
4 It is only given to the fire to be consumed; the fire consumes that which is yearly pruned of it, and it is utterly gone. Will it be useful for [any] work?
Lẹ́yìn èyí, ṣe a jù ú sínú iná gẹ́gẹ́ bí epo ìdáná, gbogbo igun rẹ̀ jóná pẹ̀lú àárín rẹ, ṣé o wà le wúlò fún nǹkan kan mọ́?
5 Not even while it is yet whole will it be [useful] for [any] work: if the fire shall have utterly consumed it, will it still be [fit] for work?
Tí kò bá wúlò fún nǹkan kan nígbà tó wà lódidi, báwo ni yóò ṣe wá wúlò nígbà tí iná ti jó o, tó sì dúdú nítorí èéfín?
6 Therefore say, Thus says the Lord, As the vine tree among the trees of the forest, which I have given up to the fire to be consumed, so have I given up the inhabitants of Jerusalem.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bí mo ṣe sọ igi àjàrà tó wà láàrín àwọn igi inú igbó yòókù di igi ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe ṣe gbogbo ènìyàn tó ń gbé Jerusalẹmu.
7 And I will set my face against them; they shall go forth of the fire, and [yet] fire shall devour them; and they shall know that I am the Lord, when I have set my face against them.
Èmi yóò dojúkọ wọ́n. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ti jáde kúrò nínú iná kan, síbẹ̀ iná mìíràn yóò pàpà jó wọn. Nígbà tí mo bá sì dojúkọ wọ́n, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
8 And I will give up the land to ruin, because they have utterly transgressed, says the Lord.
Èmi yóò sọ ilé náà di ahoro nítorí ìwà àìṣòótọ́ wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.”

< Jezekiel 15 >