< Psalms 46 >

1 To the chief Musician for the sons of Korah, A Song upon Alamoth. God [is] our refuge and strength, a very present help in trouble.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. Orin. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.
2 Therefore will not we fear, though the earth be removed, and though the mountains be carried into the midst of the sea;
Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí, tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.
3 [Though] the waters thereof roar [and] be troubled, [though] the mountains shake with the swelling thereof. (Selah)
Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. (Sela)
4 [There is] a river, the streams whereof shall make glad the city of God, the holy [place] of the tabernacles of the most High.
Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn, ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.
5 God [is] in the midst of her; she shall not be moved: God shall help her, [and that] right early.
Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀: Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.
6 The heathen raged, the kingdoms were moved: he uttered his voice, the earth melted.
Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú, ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.
7 The LORD of hosts [is] with us; the God of Jacob [is] our refuge. (Selah)
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa, Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.
8 Come, behold the works of the LORD, what desolations he hath made in the earth.
Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwa irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.
9 He maketh wars to cease unto the end of the earth; he breaketh the bow, and cutteth the spear in sunder; he burneth the chariot in the fire.
O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná.
10 Be still, and know that I [am] God: I will be exalted among the heathen, I will be exalted in the earth.
Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run. A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè, a ó gbé mi ga ní ayé.
11 The LORD of hosts [is] with us; the God of Jacob [is] our refuge. (Selah)
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa; Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.

< Psalms 46 >