< Psalms 129 >
1 A Song of degrees. Many a time have they afflicted me from my youth, may Israel now say:
Orin fún ìgòkè. “Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá,” jẹ́ kí Israẹli kí ó wí nísinsin yìí;
2 Many a time have they afflicted me from my youth: yet they have not prevailed against me.
“Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá; síbẹ̀ wọn kò tí ì borí mi.
3 The plowers plowed upon my back: they made long their furrows.
Àwọn awalẹ̀ walẹ̀ sí ẹ̀yìn mi: wọ́n sì la aporo wọn gígùn.
4 The LORD [is] righteous: he hath cut asunder the cords of the wicked.
Olódodo ni Olúwa: ó ti ké okùn àwọn ènìyàn búburú kúrò.”
5 Let them all be confounded and turned back that hate Zion.
Kí gbogbo àwọn tí ó kórìíra Sioni kí ó dààmú, kí wọn kí ó sì yí ẹ̀yìn padà.
6 Let them be as the grass [upon] the housetops, which withereth afore it groweth up:
Kí wọn kí ó dàbí koríko orí ilẹ̀ tí ó gbẹ dànù kí ó tó dàgbàsókè,
7 Wherewith the mower filleth not his hand; nor he that bindeth sheaves his bosom.
èyí tí olóko pípa kó kún ọwọ́ rẹ̀: bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń di ìtí, kó kún apá rẹ̀.
8 Neither do they which go by say, The blessing of the LORD [be] upon you: we bless you in the name of the LORD.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ń kọjá lọ kò wí pé, ìbùkún Olúwa kí ó pẹ̀lú yín: àwa ń súre fún yin ní orúkọ Olúwa.