< Psalms 105 >

1 O give thanks unto the LORD; call upon his name: make known his deeds among the people.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Sing unto him, sing psalms unto him: talk ye of all his wondrous works.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Glory ye in his holy name: let the heart of them rejoice that seek the LORD.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Seek the LORD, and his strength: seek his face evermore.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Remember his marvellous works that he hath done; his wonders, and the judgments of his mouth;
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 O ye seed of Abraham his servant, ye children of Jacob his chosen.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 He [is] the LORD our God: his judgments [are] in all the earth.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 He hath remembered his covenant for ever, the word [which] he commanded to a thousand generations.
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Which [covenant] he made with Abraham, and his oath unto Isaac;
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 And confirmed the same unto Jacob for a law, [and] to Israel [for] an everlasting covenant:
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Saying, Unto thee will I give the land of Canaan, the lot of your inheritance:
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 When they were [but] a few men in number; yea, very few, and strangers in it.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 When they went from one nation to another, from [one] kingdom to another people;
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 He suffered no man to do them wrong: yea, he reproved kings for their sakes;
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 [Saying], Touch not mine anointed, and do my prophets no harm.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Moreover he called for a famine upon the land: he brake the whole staff of bread.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 He sent a man before them, [even] Joseph, [who] was sold for a servant:
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Whose feet they hurt with fetters: he was laid in iron:
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Until the time that his word came: the word of the LORD tried him.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 The king sent and loosed him; [even] the ruler of the people, and let him go free.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 He made him lord of his house, and ruler of all his substance:
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 To bind his princes at his pleasure; and teach his senators wisdom.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Israel also came into Egypt; and Jacob sojourned in the land of Ham.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 And he increased his people greatly; and made them stronger than their enemies.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 He turned their heart to hate his people, to deal subtilly with his servants.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 He sent Moses his servant; [and] Aaron whom he had chosen.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 They shewed his signs among them, and wonders in the land of Ham.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 He sent darkness, and made it dark; and they rebelled not against his word.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 He turned their waters into blood, and slew their fish.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Their land brought forth frogs in abundance, in the chambers of their kings.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 He spake, and there came divers sorts of flies, [and] lice in all their coasts.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 He gave them hail for rain, [and] flaming fire in their land.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 He smote their vines also and their fig trees; and brake the trees of their coasts.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 He spake, and the locusts came, and caterpillers, and that without number,
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 And did eat up all the herbs in their land, and devoured the fruit of their ground.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 He smote also all the firstborn in their land, the chief of all their strength.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 He brought them forth also with silver and gold: and [there was] not one feeble [person] among their tribes.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Egypt was glad when they departed: for the fear of them fell upon them.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 He spread a cloud for a covering; and fire to give light in the night.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 [The people] asked, and he brought quails, and satisfied them with the bread of heaven.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 He opened the rock, and the waters gushed out; they ran in the dry places [like] a river.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 For he remembered his holy promise, [and] Abraham his servant.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 And he brought forth his people with joy, [and] his chosen with gladness:
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 And gave them the lands of the heathen: and they inherited the labour of the people;
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 That they might observe his statutes, and keep his laws. Praise ye the LORD.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psalms 105 >