< Isaiah 12 >

1 And in that day thou shalt say, O Yhwh, I will praise thee: though thou wast angry with me, thine anger is turned away, and thou comfortedst me.
Ní ọjọ́ náà ni ìwọ ó wí pé, “Èmi ó yìn ọ́, Olúwa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ò ti bínú sí mi ìbínú rẹ ti yí kúrò níbẹ̀ ìwọ sì ti tù mí nínú.
2 Behold, God is my salvation; I will trust, and not be afraid: for Yah Yhwh is my strength and my song; he also is become my salvation.
Nítòótọ́ Ọlọ́run ni ìgbàlà mi, èmi yóò gbẹ́kẹ̀lé e èmi kì yóò bẹ̀rù. Olúwa, Olúwa náà ni agbára à mi àti orin ìn mi, òun ti di ìgbàlà mi.”
3 Therefore with joy shall ye draw water out of the wells of salvation.
Pẹ̀lú ayọ̀ ni ìwọ yóò máa pọn omi láti inú kànga ìgbàlà.
4 And in that day shall ye say, Praise Yhwh, call upon his name, declare his doings among the people, make mention that his name is exalted.
Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò wí pé, “Fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ti ṣe kí o sì kéde pé a ti gbé orúkọ rẹ̀ ga.
5 Sing unto Yhwh; for he hath done excellent things: this is known in all the earth.
Kọ orin sí Olúwa, nítorí ó ti ṣe ohun tí ó lógo, jẹ́ kí èyí di mí mọ̀ fún gbogbo ayé.
6 Cry out and shout, thou inhabitant of Zion: for great is the Holy One of Israel in the midst of thee.
Kígbe sókè kí o sì kọrin fún ayọ̀, ẹ̀yin ènìyàn Sioni, nítorí títóbi ni ẹni mímọ́ kan ṣoṣo ti Israẹli láàrín yín.”

< Isaiah 12 >