< Psalms 79 >

1 A Psalm of Asaph. O God, the heathen are come into Thine inheritance; they have defiled Thy holy temple; they have made Jerusalem into heaps.
Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
2 They have given the dead bodies of Thy servants to be food unto the fowls of the heaven, the flesh of Thy saints unto the beasts of the earth.
Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
3 They have shed their blood like water round about Jerusalem, with none to bury them.
Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
4 We are become a taunt to our neighbours, a scorn and derision to them that are round about us.
Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
5 How long, O LORD, wilt Thou be angry for ever? How long will Thy jealousy burn like fire?
Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
6 Pour out Thy wrath upon the nations that know Thee not, and upon the kingdoms that call not upon Thy name.
Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
7 For they have devoured Jacob, and laid waste his habitation.
nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
8 Remember not against us the iniquities of our forefathers; let Thy compassions speedily come to meet us; for we are brought very low.
Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
9 Help us, O God of our salvation, for the sake of the glory of Thy name; and deliver us, and forgive our sins, for Thy name's sake.
Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
10 Wherefore should the nations say: 'Where is their God?' Let the avenging of Thy servants' blood that is shed be made known among the nations in our sight.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
11 Let the groaning of the prisoner come before Thee; according to the greatness of Thy power set free those that are appointed to death;
Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
12 And render unto our neighbours sevenfold into their bosom their reproach, wherewith they have reproached Thee, O Lord.
San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
13 So we that are Thy people and the flock of Thy pasture will give Thee thanks for ever; we will tell of Thy praise to all generations.
Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.

< Psalms 79 >