< Psalms 76 >

1 For the Leader; with string-music. A Psalm of Asaph, a Song. In Judah is God known; His name is great in Israel.
Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Asafu. Orin. Ní Juda ni a mọ Ọlọ́run; orúkọ rẹ̀ sì lágbára ní Israẹli
2 In Salem also is set His tabernacle, and His dwelling-place in Zion.
Àgọ́ rẹ̀ wà ní Salẹmu, ibùgbé rẹ̀ ni Sioni.
3 There He broke the fiery shafts of the bow; the shield, and the sword, and the battle. (Selah)
Níbẹ̀ ni ó ṣẹ́ ọfà, asà àti àwọn idà, ohun ìjà ogun. (Sela)
4 Glorious art Thou and excellent, coming down from the mountains of prey.
Ìwọ ni ògo àti ọlá, ju òkè ńlá ìkógun wọ̀nyí lọ.
5 The stout-hearted are bereft of sense, they sleep their sleep; and none of the men of might have found their hands.
A kó àwọn alágídí ọkàn ní ìkógun wọ́n sun oorun ìgbẹ̀yìn wọn; kò sí ọ̀kan nínú àwọn akọni tó lè gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè.
6 At Thy rebuke, O God of Jacob, they are cast into a dead sleep, the riders also and the horses.
Ní ìfibú rẹ, Ọlọ́run Jakọbu, àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
7 Thou, even Thou, art terrible; and who may stand in Thy sight when once Thou art angry?
Ìwọ nìkan ni ó yẹ kí a bẹ̀rù. Ta ló lé dúró níwájú rẹ, nígbà tí ìwọ bá ń bínú?
8 Thou didst cause sentence to be heard from heaven; the earth feared, and was still,
Ìwọ ń ṣe ìdájọ́ láti ọ̀run, ilé ayé bẹ̀rù, ó sì dúró jẹ́ẹ́,
9 When God arose to judgment, to save all the humble of the earth. (Selah)
nígbà tí, ìwọ Ọlọ́run, bá dìde láti ṣe ìdájọ́, láti gba àwọn ẹni ìnilára ilẹ̀ náà. (Sela)
10 Surely the wrath of man shall praise Thee; the residue of wrath shalt Thou gird upon Thee.
Lóòótọ́, ìbínú rẹ sí àwọn ènìyàn ń mú ìyìn wá fún ọ, ẹni tí ó yọ nínú ìbínú rẹ ní a dá nígbà tí ìwọ bá fi ìbínú ìyókù di ara rẹ ni àmùrè.
11 Vow, and pay unto the LORD your God; let all that are round about Him bring presents unto Him that is to be feared;
Jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì mú un ṣẹ; kí gbogbo àwọn tí ó yí i ká mú ẹ̀bùn wá fún ẹni tí ó tọ́ láti bẹ̀rù.
12 He minisheth the spirit of princes; He is terrible to the kings of the earth.
Ó ké ẹ̀mí àwọn aládé kúrò; àwọn ọba ayé sì ń bẹ̀rù rẹ̀.

< Psalms 76 >